Psalms 149 (BOYCB)
1 Ẹ fi ìyìn fún OLÚWA. Ẹ kọrin tuntun sí OLÚWA.Ẹ yìn ín ní àwùjọ àwọn ènìyàn mímọ́. 2 Jẹ́ kí Israẹli kí ó ní inú dídùn sí ẹni tí ó dá ajẹ́ kí àwọn ọmọ Sioni kí ó níayọ̀ nínú ọba wọn. 3 Jẹ́ kí wọn kí ó fi ijó yin orúkọ rẹ̀jẹ́ kí wọn kí ó fi ohun èlò orin kọrin ìyìn sí i. 4 Nítorí OLÚWA ní inú dídùn sí àwọn ènìyàn rẹ̀ó fi ìgbàlà dé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ládé. 5 Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mímọ́ kí ó yọ̀ nínú ọlá rẹ̀kí wọn kí ó máa kọrin fún ayọ̀ ní orí ibùsùn wọn. 6 Kí ìyìn Ọlọ́run kí ó wà ní ẹnu wọnàti idà olójú méjì ní ọwọ́ wọn. 7 Láti gba ẹ̀san lára àwọn orílẹ̀-èdè,àti ìjìyà lára àwọn ènìyàn, 8 láti fi ẹ̀wọ̀n de àwọn ọba wọnàti láti fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀irin de àwọn ọlọ́lá wọn. 9 Láti ṣe ìdájọ́ tí àkọsílẹ̀ rẹ̀ sí wọnèyí ni ògo àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún OLÚWA.