Deuteronomy 26 (BOYCB)

1 Nígbà tí ìwọ bá wọ ilẹ̀ tí OLÚWA Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìní tí ìwọ sì ti jogún, tí ìwọ sì ti ń gbé níbẹ̀, 2 mú díẹ̀ nínú ohun tí o pèsè láti inú erùpẹ̀ ilẹ̀ náà tí OLÚWA Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ, kó wọn sínú agbọ̀n. Nígbà náà kí o lọ sí ibi tí OLÚWA Ọlọ́run rẹ yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibi tí orúkọ rẹ̀ yóò máa gbé. 3 Kí o sì sọ fun àlùfáà tí ó wà ní ibi iṣẹ́ ní àsìkò náà, pé, “Mo sọ ọ́ di mí mọ̀ fún OLÚWA Ọlọ́run rẹ pé mo ti wá sí ilẹ̀ tí OLÚWA búra fún àwọn baba wa.” 4 Àlùfáà yóò gbé agbọ̀n náà kúrò ní ọwọ́ rẹ, yóò sì gbé e kalẹ̀ níwájú pẹpẹ OLÚWA Ọlọ́run rẹ. 5 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní iwájú OLÚWA Ọlọ́run rẹ pé, “Baba mi jẹ́ alárìnkiri ará Aramu, ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti pẹ̀lú ènìyàn díẹ̀, ó sì ń gbé níbẹ̀, ó sì wá di orílẹ̀-èdè olókìkí, alágbára, tí ó kún fún ọ̀pọ̀ ènìyàn. 6 Ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti ṣe àìdára sí wa, wọ́n jẹ wá ní yà, wọ́n fún wa ní iṣẹ́ líle ṣe. 7 Nígbà náà ni a kégbe pe OLÚWA Ọlọ́run àwọn baba wa, OLÚWA sì gbọ́ ohùn wa, ó sì rí ìrora, làálàá àti ìnira wa. 8 Nígbà náà ni OLÚWA mú wa jáde wá láti Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà, pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá àti iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu. 9 Ó mú wa wá síbí, ó sì fún wa ní ilẹ̀ yìí, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; 10 àti pé ní báyìí, mo mú àkọ́so ilẹ̀ tí ìwọ OLÚWA ti fún mi wá.” Ìwọ yóò gbé agbọ̀n náà síwájú OLÚWA Ọlọ́run rẹ, kí o sì wólẹ̀ níwájú u rẹ̀. 11 Ìwọ àti àwọn ọmọ Lefi àti àjèjì láàrín yín yóò máa yọ̀ nínú gbogbo oore tí OLÚWA ti fi fún ọ àti fún àwọn ará ilé rẹ. 12 Nígbà tí ìwọ bá ṣetán láti ya ìdámẹ́wàá gbogbo ohun tí o ti mú jáde ní ọdún kẹta sọ́tọ̀ sí apá kan. Ọdún ìdámẹ́wàá, ìwọ yóò fi fún ọmọ Lefi, àjèjì, aláìní baba àti opó, kí wọn kí ó lè jẹ ní àwọn ìlú rẹ, kí wọn sì yó. 13 Nígbà náà ní kí o wí fún OLÚWA Ọlọ́run rẹ pé, “Èmi ti mú ohun mímọ́ kúrò nínú ilé mi, èmi sì ti fi fún àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó, gẹ́gẹ́ bí ohun gbogbo tí ìwọ ti pàṣẹ. Èmi kò yípadà kúrò nínú àṣẹ rẹ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbàgbé ọ̀kankan nínú wọn. 14 Èmi kò jẹ lára ohun mímọ́ ní ìgbà tí mo ń ṣọ̀fọ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu nínú wọn ní ìgbà tí mo wà ní àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi nínú wọn fún òkú. Èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí OLÚWA Ọlọ́run mi, èmi sì ti ṣe gbogbo ohun tí ó pàṣẹ fún mi. 15 Wo ilẹ̀ láti ọ̀run wá, ibùgbé mímọ́ rẹ, kí o sì bùkún fún àwọn ènìyàn Israẹli, àti fún ilẹ̀ náà tí ìwọ ti fi fún wa, bí ìwọ ti búra fún àwọn baba ńlá wa, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin.” 16 OLÚWA Ọlọ́run rẹ pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa tẹ̀lé àwọn ìlànà àti òfin, kí o sì máa ṣe wọ́n pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo àyà rẹ. 17 Ìwọ jẹ́wọ́ OLÚWA ní òní pé OLÚWA ni Ọlọ́run rẹ, àti pé ìwọ yóò máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, àti pé ìwọ yóò máa pa ìlànà rẹ̀, àṣẹ rẹ̀ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti pé ìwọ yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí i. 18 Ní òní ni OLÚWA jẹ́wọ́ rẹ pé ìwọ ni ènìyàn òun, ilé ìṣúra rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí, àti pé ìwọ yóò máa pa gbogbo àṣẹ rẹ̀ mọ́. 19 Òun sì jẹ́wọ́ pé, òun yóò gbé ọ sókè ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí òun ti dá lọ, ní ìyìn, ní òkìkí àti ní ọlá; kí ìwọ kí ó le jẹ́ ènìyàn mímọ́ sí OLÚWA Ọlọ́run rẹ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí.

In Other Versions

Deuteronomy 26 in the ANGEFD

Deuteronomy 26 in the ANTPNG2D

Deuteronomy 26 in the AS21

Deuteronomy 26 in the BAGH

Deuteronomy 26 in the BBPNG

Deuteronomy 26 in the BBT1E

Deuteronomy 26 in the BDS

Deuteronomy 26 in the BEV

Deuteronomy 26 in the BHAD

Deuteronomy 26 in the BIB

Deuteronomy 26 in the BLPT

Deuteronomy 26 in the BNT

Deuteronomy 26 in the BNTABOOT

Deuteronomy 26 in the BNTLV

Deuteronomy 26 in the BOATCB

Deuteronomy 26 in the BOATCB2

Deuteronomy 26 in the BOBCV

Deuteronomy 26 in the BOCNT

Deuteronomy 26 in the BOECS

Deuteronomy 26 in the BOGWICC

Deuteronomy 26 in the BOHCB

Deuteronomy 26 in the BOHCV

Deuteronomy 26 in the BOHLNT

Deuteronomy 26 in the BOHNTLTAL

Deuteronomy 26 in the BOICB

Deuteronomy 26 in the BOILNTAP

Deuteronomy 26 in the BOITCV

Deuteronomy 26 in the BOKCV

Deuteronomy 26 in the BOKCV2

Deuteronomy 26 in the BOKHWOG

Deuteronomy 26 in the BOKSSV

Deuteronomy 26 in the BOLCB

Deuteronomy 26 in the BOLCB2

Deuteronomy 26 in the BOMCV

Deuteronomy 26 in the BONAV

Deuteronomy 26 in the BONCB

Deuteronomy 26 in the BONLT

Deuteronomy 26 in the BONUT2

Deuteronomy 26 in the BOPLNT

Deuteronomy 26 in the BOSCB

Deuteronomy 26 in the BOSNC

Deuteronomy 26 in the BOTLNT

Deuteronomy 26 in the BOVCB

Deuteronomy 26 in the BPBB

Deuteronomy 26 in the BPH

Deuteronomy 26 in the BSB

Deuteronomy 26 in the CCB

Deuteronomy 26 in the CUV

Deuteronomy 26 in the CUVS

Deuteronomy 26 in the DBT

Deuteronomy 26 in the DGDNT

Deuteronomy 26 in the DHNT

Deuteronomy 26 in the DNT

Deuteronomy 26 in the ELBE

Deuteronomy 26 in the EMTV

Deuteronomy 26 in the ESV

Deuteronomy 26 in the FBV

Deuteronomy 26 in the FEB

Deuteronomy 26 in the GGMNT

Deuteronomy 26 in the GNT

Deuteronomy 26 in the HARY

Deuteronomy 26 in the HNT

Deuteronomy 26 in the IRVA

Deuteronomy 26 in the IRVB

Deuteronomy 26 in the IRVG

Deuteronomy 26 in the IRVH

Deuteronomy 26 in the IRVK

Deuteronomy 26 in the IRVM

Deuteronomy 26 in the IRVM2

Deuteronomy 26 in the IRVO

Deuteronomy 26 in the IRVP

Deuteronomy 26 in the IRVT

Deuteronomy 26 in the IRVT2

Deuteronomy 26 in the IRVU

Deuteronomy 26 in the ISVN

Deuteronomy 26 in the JSNT

Deuteronomy 26 in the KAPI

Deuteronomy 26 in the KBT1ETNIK

Deuteronomy 26 in the KBV

Deuteronomy 26 in the KJV

Deuteronomy 26 in the KNFD

Deuteronomy 26 in the LBA

Deuteronomy 26 in the LBLA

Deuteronomy 26 in the LNT

Deuteronomy 26 in the LSV

Deuteronomy 26 in the MAAL

Deuteronomy 26 in the MBV

Deuteronomy 26 in the MBV2

Deuteronomy 26 in the MHNT

Deuteronomy 26 in the MKNFD

Deuteronomy 26 in the MNG

Deuteronomy 26 in the MNT

Deuteronomy 26 in the MNT2

Deuteronomy 26 in the MRS1T

Deuteronomy 26 in the NAA

Deuteronomy 26 in the NASB

Deuteronomy 26 in the NBLA

Deuteronomy 26 in the NBS

Deuteronomy 26 in the NBVTP

Deuteronomy 26 in the NET2

Deuteronomy 26 in the NIV11

Deuteronomy 26 in the NNT

Deuteronomy 26 in the NNT2

Deuteronomy 26 in the NNT3

Deuteronomy 26 in the PDDPT

Deuteronomy 26 in the PFNT

Deuteronomy 26 in the RMNT

Deuteronomy 26 in the SBIAS

Deuteronomy 26 in the SBIBS

Deuteronomy 26 in the SBIBS2

Deuteronomy 26 in the SBICS

Deuteronomy 26 in the SBIDS

Deuteronomy 26 in the SBIGS

Deuteronomy 26 in the SBIHS

Deuteronomy 26 in the SBIIS

Deuteronomy 26 in the SBIIS2

Deuteronomy 26 in the SBIIS3

Deuteronomy 26 in the SBIKS

Deuteronomy 26 in the SBIKS2

Deuteronomy 26 in the SBIMS

Deuteronomy 26 in the SBIOS

Deuteronomy 26 in the SBIPS

Deuteronomy 26 in the SBISS

Deuteronomy 26 in the SBITS

Deuteronomy 26 in the SBITS2

Deuteronomy 26 in the SBITS3

Deuteronomy 26 in the SBITS4

Deuteronomy 26 in the SBIUS

Deuteronomy 26 in the SBIVS

Deuteronomy 26 in the SBT

Deuteronomy 26 in the SBT1E

Deuteronomy 26 in the SCHL

Deuteronomy 26 in the SNT

Deuteronomy 26 in the SUSU

Deuteronomy 26 in the SUSU2

Deuteronomy 26 in the SYNO

Deuteronomy 26 in the TBIAOTANT

Deuteronomy 26 in the TBT1E

Deuteronomy 26 in the TBT1E2

Deuteronomy 26 in the TFTIP

Deuteronomy 26 in the TFTU

Deuteronomy 26 in the TGNTATF3T

Deuteronomy 26 in the THAI

Deuteronomy 26 in the TNFD

Deuteronomy 26 in the TNT

Deuteronomy 26 in the TNTIK

Deuteronomy 26 in the TNTIL

Deuteronomy 26 in the TNTIN

Deuteronomy 26 in the TNTIP

Deuteronomy 26 in the TNTIZ

Deuteronomy 26 in the TOMA

Deuteronomy 26 in the TTENT

Deuteronomy 26 in the UBG

Deuteronomy 26 in the UGV

Deuteronomy 26 in the UGV2

Deuteronomy 26 in the UGV3

Deuteronomy 26 in the VBL

Deuteronomy 26 in the VDCC

Deuteronomy 26 in the YALU

Deuteronomy 26 in the YAPE

Deuteronomy 26 in the YBVTP

Deuteronomy 26 in the ZBP