Exodus 1 (BOYCB)

1 Ìwọ̀nyí ni àwọn orúkọ ọmọ Israẹli tí wọ́n bá Jakọbu lọ sí Ejibiti, ẹnìkọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ìdílé rẹ̀: 2 Reubeni, Simeoni, Lefi àti Juda; 3 Isakari, Sebuluni àti Benjamini; 4 Dani àti Naftali;Gadi àti Aṣeri. 5 Àwọn ìran Jakọbu sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Josẹfu sì ti wà ní Ejibiti. 6 Wàyí o, Josẹfu àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú, 7 ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà. 8 Nígbà náà ni ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti. 9 Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, “Ẹ wò ó, àwọn ará Israẹli ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa. 10 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lo ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí láti dá wọn lẹ́kun, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ wọn yóò túbọ̀ máa pọ̀ sí i. Bí ogun bá sì bẹ́ sílẹ̀, wọn yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ọ̀tá wa, wọn yóò sì da ojú ìjà kọ wá, wọn yóò sì sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ yìí.” 11 Nítorí náà, wọ́n yan àwọn ọ̀gá akóniṣiṣẹ́ lé wọn lórí láti máa ni wọ́n lára pẹ̀lú iṣẹ́ àṣekára. Wọ́n sì kọ́ Pitomi àti Ramesesi gẹ́gẹ́ bí ìlú ìṣúra pamọ́ sí fún Farao. 12 Ṣùgbọ́n bí a ti ń ni wọ́n lára tó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń pọ̀ sí i, tí wọ́n sì ń tànkálẹ̀. Nítorí náà, àwọn ará Ejibiti bẹ̀rù nítorí àwọn ará Israẹli. 13 Àwọn ará Ejibiti sì mú àwọn ọmọ Israẹli sìn ní àsìnpa. 14 Wọ́n mú wọn gbé ìgbé ayé kíkorò nípa iṣẹ́ bíríkì àti àwọn onírúurú iṣẹ́ oko; àwọn ará Ejibiti ń lò wọ́n ní ìlòkulò. 15 Ọba Ejibiti sọ fún àwọn agbẹ̀bí Heberu ti orúkọ wọn ń jẹ́ Ṣifura àti Pua pé, 16 “Nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbẹ̀bí àwọn obìnrin Heberu, tí ẹ sì kíyèsi wọn lórí ìkúnlẹ̀ ìrọbí wọn, bí ó bá jẹ́ ọkùnrin ni ọmọ náà, ẹ pa á; ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ obìnrin, ẹ jẹ́ kí ó wà láààyè.” 17 Ṣùgbọ́n àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọba Ejibiti ti wí fún wọn; wọ́n jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wà láààyè. 18 Ọba Ejibiti pe àwọn agbẹ̀bí ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí? Èéṣe tí ẹ̀yin fi dá àwọn ọmọkùnrin si?” 19 Àwọn agbẹ̀bí náà sì dá Farao lóhùn pé, “Àwọn obìnrin Heberu kò rí bí àwọn obìnrin Ejibiti, wọ́n ní agbára, wọ́n sì ti máa ń bí ọmọ kí àwọn agbẹ̀bí tó dé ọ̀dọ̀ wọn.” 20 Nítorí náà Ọlọ́run ṣàánú fún àwọn agbẹ̀bí náà, àwọn ọmọ Israẹli sì ń le sí i, wọ́n sì ń pọ̀ sí i jọjọ. 21 Nítorí pé àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, Ọlọ́run sì fún wọn ni ìdílé tiwọn. 22 Nígbà náà ni Farao pàṣẹ yìí fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ pé, “Gbogbo ọmọkùnrin tí a bí ni kí ẹ gbé jù sínú odò Naili, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọbìnrin ni kí ẹ jẹ́ kí wọn ó wà láààyè.”

In Other Versions

Exodus 1 in the ANGEFD

Exodus 1 in the ANTPNG2D

Exodus 1 in the AS21

Exodus 1 in the BAGH

Exodus 1 in the BBPNG

Exodus 1 in the BBT1E

Exodus 1 in the BDS

Exodus 1 in the BEV

Exodus 1 in the BHAD

Exodus 1 in the BIB

Exodus 1 in the BLPT

Exodus 1 in the BNT

Exodus 1 in the BNTABOOT

Exodus 1 in the BNTLV

Exodus 1 in the BOATCB

Exodus 1 in the BOATCB2

Exodus 1 in the BOBCV

Exodus 1 in the BOCNT

Exodus 1 in the BOECS

Exodus 1 in the BOGWICC

Exodus 1 in the BOHCB

Exodus 1 in the BOHCV

Exodus 1 in the BOHLNT

Exodus 1 in the BOHNTLTAL

Exodus 1 in the BOICB

Exodus 1 in the BOILNTAP

Exodus 1 in the BOITCV

Exodus 1 in the BOKCV

Exodus 1 in the BOKCV2

Exodus 1 in the BOKHWOG

Exodus 1 in the BOKSSV

Exodus 1 in the BOLCB

Exodus 1 in the BOLCB2

Exodus 1 in the BOMCV

Exodus 1 in the BONAV

Exodus 1 in the BONCB

Exodus 1 in the BONLT

Exodus 1 in the BONUT2

Exodus 1 in the BOPLNT

Exodus 1 in the BOSCB

Exodus 1 in the BOSNC

Exodus 1 in the BOTLNT

Exodus 1 in the BOVCB

Exodus 1 in the BPBB

Exodus 1 in the BPH

Exodus 1 in the BSB

Exodus 1 in the CCB

Exodus 1 in the CUV

Exodus 1 in the CUVS

Exodus 1 in the DBT

Exodus 1 in the DGDNT

Exodus 1 in the DHNT

Exodus 1 in the DNT

Exodus 1 in the ELBE

Exodus 1 in the EMTV

Exodus 1 in the ESV

Exodus 1 in the FBV

Exodus 1 in the FEB

Exodus 1 in the GGMNT

Exodus 1 in the GNT

Exodus 1 in the HARY

Exodus 1 in the HNT

Exodus 1 in the IRVA

Exodus 1 in the IRVB

Exodus 1 in the IRVG

Exodus 1 in the IRVH

Exodus 1 in the IRVK

Exodus 1 in the IRVM

Exodus 1 in the IRVM2

Exodus 1 in the IRVO

Exodus 1 in the IRVP

Exodus 1 in the IRVT

Exodus 1 in the IRVT2

Exodus 1 in the IRVU

Exodus 1 in the ISVN

Exodus 1 in the JSNT

Exodus 1 in the KAPI

Exodus 1 in the KBT1ETNIK

Exodus 1 in the KBV

Exodus 1 in the KJV

Exodus 1 in the KNFD

Exodus 1 in the LBA

Exodus 1 in the LBLA

Exodus 1 in the LNT

Exodus 1 in the LSV

Exodus 1 in the MAAL

Exodus 1 in the MBV

Exodus 1 in the MBV2

Exodus 1 in the MHNT

Exodus 1 in the MKNFD

Exodus 1 in the MNG

Exodus 1 in the MNT

Exodus 1 in the MNT2

Exodus 1 in the MRS1T

Exodus 1 in the NAA

Exodus 1 in the NASB

Exodus 1 in the NBLA

Exodus 1 in the NBS

Exodus 1 in the NBVTP

Exodus 1 in the NET2

Exodus 1 in the NIV11

Exodus 1 in the NNT

Exodus 1 in the NNT2

Exodus 1 in the NNT3

Exodus 1 in the PDDPT

Exodus 1 in the PFNT

Exodus 1 in the RMNT

Exodus 1 in the SBIAS

Exodus 1 in the SBIBS

Exodus 1 in the SBIBS2

Exodus 1 in the SBICS

Exodus 1 in the SBIDS

Exodus 1 in the SBIGS

Exodus 1 in the SBIHS

Exodus 1 in the SBIIS

Exodus 1 in the SBIIS2

Exodus 1 in the SBIIS3

Exodus 1 in the SBIKS

Exodus 1 in the SBIKS2

Exodus 1 in the SBIMS

Exodus 1 in the SBIOS

Exodus 1 in the SBIPS

Exodus 1 in the SBISS

Exodus 1 in the SBITS

Exodus 1 in the SBITS2

Exodus 1 in the SBITS3

Exodus 1 in the SBITS4

Exodus 1 in the SBIUS

Exodus 1 in the SBIVS

Exodus 1 in the SBT

Exodus 1 in the SBT1E

Exodus 1 in the SCHL

Exodus 1 in the SNT

Exodus 1 in the SUSU

Exodus 1 in the SUSU2

Exodus 1 in the SYNO

Exodus 1 in the TBIAOTANT

Exodus 1 in the TBT1E

Exodus 1 in the TBT1E2

Exodus 1 in the TFTIP

Exodus 1 in the TFTU

Exodus 1 in the TGNTATF3T

Exodus 1 in the THAI

Exodus 1 in the TNFD

Exodus 1 in the TNT

Exodus 1 in the TNTIK

Exodus 1 in the TNTIL

Exodus 1 in the TNTIN

Exodus 1 in the TNTIP

Exodus 1 in the TNTIZ

Exodus 1 in the TOMA

Exodus 1 in the TTENT

Exodus 1 in the UBG

Exodus 1 in the UGV

Exodus 1 in the UGV2

Exodus 1 in the UGV3

Exodus 1 in the VBL

Exodus 1 in the VDCC

Exodus 1 in the YALU

Exodus 1 in the YAPE

Exodus 1 in the YBVTP

Exodus 1 in the ZBP