Exodus 20 (BOYCB)

1 Ọlọ́run sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí pé, 2 “Èmi ni OLÚWA Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá. 3 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi. 4 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀. 5 Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi OLÚWA Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi. 6 Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́. 7 Ẹ má ṣe ṣi orúkọ OLÚWA Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi. 8 Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́. 9 Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ, 10 ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi OLÚWA Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti ẹran ọ̀sìn rẹ, àti àlejò rẹ, tí ń bẹ nínú ibodè rẹ. 11 Nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni OLÚWA dá ọ̀run àti ayé, òkun àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn, ó sì sinmi ní ọjọ́ keje: nítorí náà ni OLÚWA ṣe bùkún ọjọ́ ìsinmi tí ó sì yà á sí mímọ́. 12 Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́ ní orí ilẹ̀ tí OLÚWA Ọlọ́run rẹ fi fún ọ. 13 Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn. 14 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà. 15 Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè. 16 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ. 17 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéjì rẹ. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéjì rẹ.” 18 Nígbà tí àwọn ènìyàn náà rí mọ̀nàmọ́ná tí wọ́n sí gbọ́ ohùn ìpè àti èéfín tí ń rú láti orí òkè, tí wọ́n sì gbọ́ sísán àrá, dídún ìpè kíkankíkan; wọ́n dúró ní òkèrè wọ́n sì ń gbọ̀n ṣìgàṣìgà fún ìbẹ̀rù. 19 Wọ́n wí fún Mose pé, “Ìwọ fúnra rẹ̀ máa bá wa sọ̀rọ̀, àwa yóò sì gbọ́. Má ṣe jẹ́ kí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ kí ó bá wa sọ̀rọ̀, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò kú.” 20 Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù. Ọlọ́run wá láti dán an yín wò, kí ẹ̀rù Ọlọ́run kí ó lè máa wà ní ara yín, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣẹ̀.” 21 Àwọn ènìyàn sì dúró ní òkèèrè nígbà tí Mose súnmọ́ ibi òkùnkùn biribiri níbi tí Ọlọ́run wà. 22 OLÚWA sì sọ fún Mose pé, “Sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ará Israẹli, ‘Ẹ̀yin ti rí i fúnra yín bí èmi ti bá a yín sọ̀rọ̀ láti ọ̀run wá. 23 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ sin ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi: ẹ̀yin kò gbọdọ̀ rọ ọlọ́run fàdákà tàbí ọlọ́run wúrà fún ara yín. 24 “ ‘Pẹpẹ erùpẹ̀ ni kí ìwọ mọ fún mi. Ní orí pẹpẹ yìí ni kí ìwọ ti máa rú ẹbọ sísun rẹ sí mi àti ẹbọ àlàáfíà rẹ, àgùntàn rẹ, ewúrẹ́ àti akọ màlúù rẹ. Ní ibi gbogbo tí mo gbé fi ìrántí orúkọ mi sí, èmi yóò sì máa tọ̀ ọ́ wá, èmi yóò sì máa bùkún ọ níbẹ̀. 25 Bí ìwọ bá ṣe pẹpẹ òkúta fún mi, má ṣe fi òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ kọ́ ọ, nítorí bí ìwọ bá lo ohun ọnà rẹ lórí rẹ̀, ìwọ sọ ọ di àìmọ́. 26 Ìwọ kò gbọdọ̀ gun àkàsọ̀ lọ sí ibi pẹpẹ mi, kí àwọn ènìyàn má ba à máa wo ìhòhò rẹ láti abẹ́ aṣọ tí ìwọ wọ̀ nígbà tí ìwọ bá ń gòkè lọ sí ibi pẹpẹ.’

In Other Versions

Exodus 20 in the ANGEFD

Exodus 20 in the ANTPNG2D

Exodus 20 in the AS21

Exodus 20 in the BAGH

Exodus 20 in the BBPNG

Exodus 20 in the BBT1E

Exodus 20 in the BDS

Exodus 20 in the BEV

Exodus 20 in the BHAD

Exodus 20 in the BIB

Exodus 20 in the BLPT

Exodus 20 in the BNT

Exodus 20 in the BNTABOOT

Exodus 20 in the BNTLV

Exodus 20 in the BOATCB

Exodus 20 in the BOATCB2

Exodus 20 in the BOBCV

Exodus 20 in the BOCNT

Exodus 20 in the BOECS

Exodus 20 in the BOGWICC

Exodus 20 in the BOHCB

Exodus 20 in the BOHCV

Exodus 20 in the BOHLNT

Exodus 20 in the BOHNTLTAL

Exodus 20 in the BOICB

Exodus 20 in the BOILNTAP

Exodus 20 in the BOITCV

Exodus 20 in the BOKCV

Exodus 20 in the BOKCV2

Exodus 20 in the BOKHWOG

Exodus 20 in the BOKSSV

Exodus 20 in the BOLCB

Exodus 20 in the BOLCB2

Exodus 20 in the BOMCV

Exodus 20 in the BONAV

Exodus 20 in the BONCB

Exodus 20 in the BONLT

Exodus 20 in the BONUT2

Exodus 20 in the BOPLNT

Exodus 20 in the BOSCB

Exodus 20 in the BOSNC

Exodus 20 in the BOTLNT

Exodus 20 in the BOVCB

Exodus 20 in the BPBB

Exodus 20 in the BPH

Exodus 20 in the BSB

Exodus 20 in the CCB

Exodus 20 in the CUV

Exodus 20 in the CUVS

Exodus 20 in the DBT

Exodus 20 in the DGDNT

Exodus 20 in the DHNT

Exodus 20 in the DNT

Exodus 20 in the ELBE

Exodus 20 in the EMTV

Exodus 20 in the ESV

Exodus 20 in the FBV

Exodus 20 in the FEB

Exodus 20 in the GGMNT

Exodus 20 in the GNT

Exodus 20 in the HARY

Exodus 20 in the HNT

Exodus 20 in the IRVA

Exodus 20 in the IRVB

Exodus 20 in the IRVG

Exodus 20 in the IRVH

Exodus 20 in the IRVK

Exodus 20 in the IRVM

Exodus 20 in the IRVM2

Exodus 20 in the IRVO

Exodus 20 in the IRVP

Exodus 20 in the IRVT

Exodus 20 in the IRVT2

Exodus 20 in the IRVU

Exodus 20 in the ISVN

Exodus 20 in the JSNT

Exodus 20 in the KAPI

Exodus 20 in the KBT1ETNIK

Exodus 20 in the KBV

Exodus 20 in the KJV

Exodus 20 in the KNFD

Exodus 20 in the LBA

Exodus 20 in the LBLA

Exodus 20 in the LNT

Exodus 20 in the LSV

Exodus 20 in the MAAL

Exodus 20 in the MBV

Exodus 20 in the MBV2

Exodus 20 in the MHNT

Exodus 20 in the MKNFD

Exodus 20 in the MNG

Exodus 20 in the MNT

Exodus 20 in the MNT2

Exodus 20 in the MRS1T

Exodus 20 in the NAA

Exodus 20 in the NASB

Exodus 20 in the NBLA

Exodus 20 in the NBS

Exodus 20 in the NBVTP

Exodus 20 in the NET2

Exodus 20 in the NIV11

Exodus 20 in the NNT

Exodus 20 in the NNT2

Exodus 20 in the NNT3

Exodus 20 in the PDDPT

Exodus 20 in the PFNT

Exodus 20 in the RMNT

Exodus 20 in the SBIAS

Exodus 20 in the SBIBS

Exodus 20 in the SBIBS2

Exodus 20 in the SBICS

Exodus 20 in the SBIDS

Exodus 20 in the SBIGS

Exodus 20 in the SBIHS

Exodus 20 in the SBIIS

Exodus 20 in the SBIIS2

Exodus 20 in the SBIIS3

Exodus 20 in the SBIKS

Exodus 20 in the SBIKS2

Exodus 20 in the SBIMS

Exodus 20 in the SBIOS

Exodus 20 in the SBIPS

Exodus 20 in the SBISS

Exodus 20 in the SBITS

Exodus 20 in the SBITS2

Exodus 20 in the SBITS3

Exodus 20 in the SBITS4

Exodus 20 in the SBIUS

Exodus 20 in the SBIVS

Exodus 20 in the SBT

Exodus 20 in the SBT1E

Exodus 20 in the SCHL

Exodus 20 in the SNT

Exodus 20 in the SUSU

Exodus 20 in the SUSU2

Exodus 20 in the SYNO

Exodus 20 in the TBIAOTANT

Exodus 20 in the TBT1E

Exodus 20 in the TBT1E2

Exodus 20 in the TFTIP

Exodus 20 in the TFTU

Exodus 20 in the TGNTATF3T

Exodus 20 in the THAI

Exodus 20 in the TNFD

Exodus 20 in the TNT

Exodus 20 in the TNTIK

Exodus 20 in the TNTIL

Exodus 20 in the TNTIN

Exodus 20 in the TNTIP

Exodus 20 in the TNTIZ

Exodus 20 in the TOMA

Exodus 20 in the TTENT

Exodus 20 in the UBG

Exodus 20 in the UGV

Exodus 20 in the UGV2

Exodus 20 in the UGV3

Exodus 20 in the VBL

Exodus 20 in the VDCC

Exodus 20 in the YALU

Exodus 20 in the YAPE

Exodus 20 in the YBVTP

Exodus 20 in the ZBP