Exodus 5 (BOYCB)

1 Lẹ́yìn náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí OLÚWA, Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó lè ṣe àjọ mi ní ijù.’ ” 2 Farao dáhùn wí pé, “Ta ni OLÚWA, tí èmi yóò fi gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, tí èmi yóò fi jẹ́ kí Israẹli ó lọ? Èmi kò mọ OLÚWA, èmi kò sì ní jẹ́ kí Israẹli ó lọ.” 3 Lẹ́yìn náà ni wọ́n wí pé, “Ọlọ́run àwọn Heberu tí pàdé wa. Ní ìsinsin yìí, jẹ́ kí a lọ ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sínú aginjù láti rú ẹbọ sí OLÚWA Ọlọ́run wa, kí Ó má ba á fi àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí idà bá wa jà.” 4 Ṣùgbọ́n ọba Ejibiti sọ wí pé, “Mose àti Aaroni, èéṣe ti ẹ̀yin fi mú àwọn ènìyàn kúrò lẹ́nu iṣẹ́ wọn? Ẹ padà sẹ́nu iṣẹ́ yín.” 5 Nígbà náà ni Farao sọ pé, “Ẹ wò ó àwọn ènìyàn náà ti pọ̀ sí ì nílẹ̀ yìí ní ìsinsin yìí, ẹ̀yin sì ń dá wọn dúró láti máa bá iṣẹ́ lọ.” 6 Ní ọjọ́ yìí kan náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn akóniṣiṣẹ́ àti àwọn ti ń ṣe alábojútó iṣẹ́ lórí àwọn ènìyàn. 7 “Ẹ̀yin kò ní láti pèsè koríko gbígbẹ fún bíríkì sísun mọ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí; ẹ jẹ́ kí wọn máa wá koríko gbígbẹ fún ara wọn. 8 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn ó ṣe iye bíríkì kan náà bí ì ti àtẹ̀yìnwá, kí ẹ má ṣe dín iye rẹ̀ kú. Ọ̀lẹ ni wọ́n, ìwà ọ̀lẹ yìí náà ló mú wọn pariwo pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ, kí a sì rú ẹbọ sí Ọlọ́run wa.’ 9 Ẹ mú iṣẹ́ náà le fún wọn, kí wọn bá a le è tẹramọ́ iṣẹ́ wọn, ẹ má fi ààyè gba irọ́ wọn.” 10 Ní ìgbà náà ni àwọn akóniṣiṣẹ́ àti àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ jáde tọ̀ wọ́n lọ láti sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Èyí ni ohun tí Farao sọ, ‘Èmi kò ní fún un yín ni koríko gbígbẹ mọ́. 11 Ẹ lọ wá koríko gbígbẹ ni ibi tí ẹ bá ti lè rí i, ṣùgbọ́n iṣẹ́ yín kí yóò dínkù.’ ” 12 Gbogbo wọn sí fọ́n káàkiri ni ilẹ̀ Ejibiti láti sa ìdì koríko tí wọn yóò lò bí ì koríko gbígbẹ fún sísun bíríkì. 13 Àwọn akóniṣiṣẹ́ sì ń ni wọ́n lára, wọ́n wí pé, “Ẹ parí iṣẹ́ tí ẹ ni láti ṣe fún ọjọ́ kan bí ìgbà ti a ń fún un yin ní koríko gbígbẹ.” 14 Àwọn alábojútó iṣẹ́ tí àwọn akóniṣiṣẹ́ Farao yàn lára ọmọ Israẹli ni wọn ń lù, tí wọn sì ń béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò ṣe iye bíríkì ti ẹ̀yin ń ṣe ní àná ní òní bí i tí àtẹ̀yìnwá?” 15 Nígbà náà ni àwọn alábojútó iṣẹ́ tí a yàn lára àwọn ọmọ Israẹli tọ Farao lọ láti lọ bẹ̀bẹ̀ pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ọwọ́ líle mú àwa ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ báyìí? 16 Wọn kò fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni koríko gbígbẹ, síbẹ̀ wọn sọ fún wa pé, ‘Ẹ ṣe bíríkì!’ Wọ́n na àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣùgbọ́n ẹ̀bi náà wá láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.” 17 Farao sí dáhùn wí pé, “Ọ̀lẹ ni yín, ọ̀lẹ! Èyí ni ó mú kí ẹ̀yin máa sọ ní ìgbà gbogbo pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ, kí a sì rú ẹbọ sí OLÚWA.’ 18 Nísinsin yìí ẹ padà lọ sí ẹnu iṣẹ́ yín, a kò ní fún un yín ni koríko gbígbẹ, síbẹ̀ ẹ gbọdọ̀ ṣe iye bíríkì tí ó yẹ kí ẹ ṣe.” 19 Àwọn ọmọ Israẹli tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ mọ̀ dájú wí pé àwọn ti wà nínú wàhálà ńlá ní ìgbà tí a sọ fún wọn pé, “Ẹ kò ní láti dín iye bíríkì tí ẹ ń ṣe ni ojoojúmọ́ kù.” 20 Ní ìgbà tí wọ́n kúrò ni ọ̀dọ̀ Farao wọ́n rí Mose àti Aaroni tí ó dúró láti pàdé wọn. 21 Wọn sì wí pé, “Kí OLÚWA kí ó wò yín, kí ó sì ṣe ìdájọ́! Ẹ̀yin ti mú wa dàbí òórùn búburú fún Farao àti àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀, ẹ sì ti fún wọn ni idà láti fi pa wá.” 22 Mose padà tọ OLÚWA lọ, ó sì wí pé, “OLÚWA, èéṣe tí ìwọ fi mú ìyọnu wá sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Ṣe torí èyí ni ìwọ fi rán mi? 23 Láti ìgbà ti mo ti tọ Farao lọ láti bá a sọ̀rọ̀ ni orúkọ rẹ ni ó ti mú ìyọnu wá sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì gba àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀ rárá.”

In Other Versions

Exodus 5 in the ANGEFD

Exodus 5 in the ANTPNG2D

Exodus 5 in the AS21

Exodus 5 in the BAGH

Exodus 5 in the BBPNG

Exodus 5 in the BBT1E

Exodus 5 in the BDS

Exodus 5 in the BEV

Exodus 5 in the BHAD

Exodus 5 in the BIB

Exodus 5 in the BLPT

Exodus 5 in the BNT

Exodus 5 in the BNTABOOT

Exodus 5 in the BNTLV

Exodus 5 in the BOATCB

Exodus 5 in the BOATCB2

Exodus 5 in the BOBCV

Exodus 5 in the BOCNT

Exodus 5 in the BOECS

Exodus 5 in the BOGWICC

Exodus 5 in the BOHCB

Exodus 5 in the BOHCV

Exodus 5 in the BOHLNT

Exodus 5 in the BOHNTLTAL

Exodus 5 in the BOICB

Exodus 5 in the BOILNTAP

Exodus 5 in the BOITCV

Exodus 5 in the BOKCV

Exodus 5 in the BOKCV2

Exodus 5 in the BOKHWOG

Exodus 5 in the BOKSSV

Exodus 5 in the BOLCB

Exodus 5 in the BOLCB2

Exodus 5 in the BOMCV

Exodus 5 in the BONAV

Exodus 5 in the BONCB

Exodus 5 in the BONLT

Exodus 5 in the BONUT2

Exodus 5 in the BOPLNT

Exodus 5 in the BOSCB

Exodus 5 in the BOSNC

Exodus 5 in the BOTLNT

Exodus 5 in the BOVCB

Exodus 5 in the BPBB

Exodus 5 in the BPH

Exodus 5 in the BSB

Exodus 5 in the CCB

Exodus 5 in the CUV

Exodus 5 in the CUVS

Exodus 5 in the DBT

Exodus 5 in the DGDNT

Exodus 5 in the DHNT

Exodus 5 in the DNT

Exodus 5 in the ELBE

Exodus 5 in the EMTV

Exodus 5 in the ESV

Exodus 5 in the FBV

Exodus 5 in the FEB

Exodus 5 in the GGMNT

Exodus 5 in the GNT

Exodus 5 in the HARY

Exodus 5 in the HNT

Exodus 5 in the IRVA

Exodus 5 in the IRVB

Exodus 5 in the IRVG

Exodus 5 in the IRVH

Exodus 5 in the IRVK

Exodus 5 in the IRVM

Exodus 5 in the IRVM2

Exodus 5 in the IRVO

Exodus 5 in the IRVP

Exodus 5 in the IRVT

Exodus 5 in the IRVT2

Exodus 5 in the IRVU

Exodus 5 in the ISVN

Exodus 5 in the JSNT

Exodus 5 in the KAPI

Exodus 5 in the KBT1ETNIK

Exodus 5 in the KBV

Exodus 5 in the KJV

Exodus 5 in the KNFD

Exodus 5 in the LBA

Exodus 5 in the LBLA

Exodus 5 in the LNT

Exodus 5 in the LSV

Exodus 5 in the MAAL

Exodus 5 in the MBV

Exodus 5 in the MBV2

Exodus 5 in the MHNT

Exodus 5 in the MKNFD

Exodus 5 in the MNG

Exodus 5 in the MNT

Exodus 5 in the MNT2

Exodus 5 in the MRS1T

Exodus 5 in the NAA

Exodus 5 in the NASB

Exodus 5 in the NBLA

Exodus 5 in the NBS

Exodus 5 in the NBVTP

Exodus 5 in the NET2

Exodus 5 in the NIV11

Exodus 5 in the NNT

Exodus 5 in the NNT2

Exodus 5 in the NNT3

Exodus 5 in the PDDPT

Exodus 5 in the PFNT

Exodus 5 in the RMNT

Exodus 5 in the SBIAS

Exodus 5 in the SBIBS

Exodus 5 in the SBIBS2

Exodus 5 in the SBICS

Exodus 5 in the SBIDS

Exodus 5 in the SBIGS

Exodus 5 in the SBIHS

Exodus 5 in the SBIIS

Exodus 5 in the SBIIS2

Exodus 5 in the SBIIS3

Exodus 5 in the SBIKS

Exodus 5 in the SBIKS2

Exodus 5 in the SBIMS

Exodus 5 in the SBIOS

Exodus 5 in the SBIPS

Exodus 5 in the SBISS

Exodus 5 in the SBITS

Exodus 5 in the SBITS2

Exodus 5 in the SBITS3

Exodus 5 in the SBITS4

Exodus 5 in the SBIUS

Exodus 5 in the SBIVS

Exodus 5 in the SBT

Exodus 5 in the SBT1E

Exodus 5 in the SCHL

Exodus 5 in the SNT

Exodus 5 in the SUSU

Exodus 5 in the SUSU2

Exodus 5 in the SYNO

Exodus 5 in the TBIAOTANT

Exodus 5 in the TBT1E

Exodus 5 in the TBT1E2

Exodus 5 in the TFTIP

Exodus 5 in the TFTU

Exodus 5 in the TGNTATF3T

Exodus 5 in the THAI

Exodus 5 in the TNFD

Exodus 5 in the TNT

Exodus 5 in the TNTIK

Exodus 5 in the TNTIL

Exodus 5 in the TNTIN

Exodus 5 in the TNTIP

Exodus 5 in the TNTIZ

Exodus 5 in the TOMA

Exodus 5 in the TTENT

Exodus 5 in the UBG

Exodus 5 in the UGV

Exodus 5 in the UGV2

Exodus 5 in the UGV3

Exodus 5 in the VBL

Exodus 5 in the VDCC

Exodus 5 in the YALU

Exodus 5 in the YAPE

Exodus 5 in the YBVTP

Exodus 5 in the ZBP