Deuteronomy 6 (BOYCB)

1 Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí OLÚWA Ọlọ́run yín pàṣẹ fún mi láti kọ́ ọ yín kí ẹ lè kíyèsi i, ní ilẹ̀ náà tí ẹ ó ni lẹ́yìn tí ẹ bá kọjá a Jordani. 2 Kí ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn, lẹ́yìn wọn bá à lè bẹ̀rù OLÚWA Ọlọ́run yín, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá wà láyé, nípa pípa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ tí mo fún un yín mọ́, kí ẹ bá à lè pẹ́ lórí ilẹ̀. 3 Gbọ́ ìwọ Israẹli, kí o sì ṣọ́ra láti gbọ́rọ̀, kí ó bá à lè dára fún ọ, kí o bá à lè gbilẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ní ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, gẹ́gẹ́ bí OLÚWA Ọlọ́run àwọn baba rẹ ti ṣèlérí fún ọ. 4 Gbọ́ ìwọ Israẹli, OLÚWA Ọlọ́run wa, OLÚWA kan ni. 5 Fẹ́ràn OLÚWA Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ. 6 Àwọn àṣẹ tí mo fún un yín lónìí gbọdọ̀ máa wà lóókan àyà yín. 7 Ẹ fi kọ́ àwọn ọmọ yín gidigidi. Bí ẹ bá jókòó nínú ilé, ẹ jíròrò nípa wọn, àti nígbà tí ẹ bá ń rìn ní ojú ọ̀nà, bí ẹ bá dùbúlẹ̀ àti nígbà tí ẹ bá dìde. 8 Ẹ so wọ́n sí ọwọ́ yín fún àmì, ẹ so ó mọ́ iwájú orí yín. 9 Kí ìwọ kí ó kọ wọ́n sára òpó ilé rẹ̀, àti sí ara ìlẹ̀kùn ọ̀nà òde rẹ. 10 Nígbà tí OLÚWA Ọlọ́run yín bá mú yín dé ilẹ̀ náà tí ó ti búra fún àwọn baba yín, fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu láti fi fún un yín, ilẹ̀ tí ó kún fún àwọn ìlú ńlá ńlá tí kì í ṣe ẹ̀yin ló kọ́ ọ, 11 àwọn ilé tí ó kún fún gbogbo ohun mèremère tí kì í ṣe ẹ̀yin ló rà wọ́n, àwọn kànga tí ẹ kò gbẹ́, àti àwọn ọgbà àjàrà àti èso olifi tí kì í ṣe ẹ̀yin ló gbìn wọ́n. Nígbà tí ẹ bá jẹ tí ẹ sì yó, 12 ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé OLÚWA, tí o mú un yín jáde láti Ejibiti wá, kúrò ní oko ẹrú. 13 Bẹ̀rù OLÚWA Ọlọ́run rẹ, Òun nìkan ni kí o sì máa sìn, búra ní orúkọ rẹ̀ nìkan. 14 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run àwọn tí ó yí i yín ká; 15 torí pé OLÚWA Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run owú ni, ìbínú rẹ̀ yóò sì run yín kúrò ní ilẹ̀ náà. 16 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dán OLÚWA Ọlọ́run yín wò bí ẹ̀yin ti dán wò ní Massa. 17 Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń pa àwọn òfin OLÚWA Ọlọ́run yín mọ́ àti àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà tí ó ti fún un yín. 18 Ẹ ṣe èyí tí ó dára tí ó sì tọ́ lójú OLÚWA, kí ó bá à lè dára fún un yín, kí ẹ̀yin bá à lè lọ láti gba ilẹ̀ dáradára náà tí Ọlọ́run ti fi ìbúra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá a yín. 19 Ẹ̀yin yóò sì ti àwọn ọ̀tá yín jáde níwájú u yín bí OLÚWA ti ṣèlérí. 20 Ní ọjọ́ iwájú, bí ọmọ rẹ bá béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin wọ̀nyí tí OLÚWA Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún ọ?” 21 Sọ fún un pé: “Ẹrú Farao ní ilẹ̀ Ejibiti ni wá tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n OLÚWA fi ọwọ́ agbára ńlá yọ wá jáde lóko ẹrú Ejibiti. 22 Lójú wa ni OLÚWA tí ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu: tí ó lágbára tí ó sì ba ni lẹ́rù: lórí Ejibiti àti Farao, àti gbogbo ènìyàn rẹ̀. 23 Ṣùgbọ́n ó mú wa jáde láti ibẹ̀ wá láti mú wa wọ inú àti láti fún wa ní ilẹ̀ tí ó ti fì búra fún àwọn baba ńlá wa. 24 OLÚWA pàṣẹ fún wa láti ṣe ìgbọ́ràn sí gbogbo ìlànà wọ̀nyí, láti bẹ̀rù OLÚWA Ọlọ́run wa, kí ó ba à lè máa dára fún wa nígbà gbogbo, kí a sì lè wà láyé, bí a ṣe wà títí di òní. 25 Bí a bá ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin wọ̀nyí mọ́ níwájú OLÚWA Ọlọ́run wa, bí ó ti pàṣẹ fún wa, èyí ni yóò máa jẹ́ òdodo wa.”

In Other Versions

Deuteronomy 6 in the ANGEFD

Deuteronomy 6 in the ANTPNG2D

Deuteronomy 6 in the AS21

Deuteronomy 6 in the BAGH

Deuteronomy 6 in the BBPNG

Deuteronomy 6 in the BBT1E

Deuteronomy 6 in the BDS

Deuteronomy 6 in the BEV

Deuteronomy 6 in the BHAD

Deuteronomy 6 in the BIB

Deuteronomy 6 in the BLPT

Deuteronomy 6 in the BNT

Deuteronomy 6 in the BNTABOOT

Deuteronomy 6 in the BNTLV

Deuteronomy 6 in the BOATCB

Deuteronomy 6 in the BOATCB2

Deuteronomy 6 in the BOBCV

Deuteronomy 6 in the BOCNT

Deuteronomy 6 in the BOECS

Deuteronomy 6 in the BOGWICC

Deuteronomy 6 in the BOHCB

Deuteronomy 6 in the BOHCV

Deuteronomy 6 in the BOHLNT

Deuteronomy 6 in the BOHNTLTAL

Deuteronomy 6 in the BOICB

Deuteronomy 6 in the BOILNTAP

Deuteronomy 6 in the BOITCV

Deuteronomy 6 in the BOKCV

Deuteronomy 6 in the BOKCV2

Deuteronomy 6 in the BOKHWOG

Deuteronomy 6 in the BOKSSV

Deuteronomy 6 in the BOLCB

Deuteronomy 6 in the BOLCB2

Deuteronomy 6 in the BOMCV

Deuteronomy 6 in the BONAV

Deuteronomy 6 in the BONCB

Deuteronomy 6 in the BONLT

Deuteronomy 6 in the BONUT2

Deuteronomy 6 in the BOPLNT

Deuteronomy 6 in the BOSCB

Deuteronomy 6 in the BOSNC

Deuteronomy 6 in the BOTLNT

Deuteronomy 6 in the BOVCB

Deuteronomy 6 in the BPBB

Deuteronomy 6 in the BPH

Deuteronomy 6 in the BSB

Deuteronomy 6 in the CCB

Deuteronomy 6 in the CUV

Deuteronomy 6 in the CUVS

Deuteronomy 6 in the DBT

Deuteronomy 6 in the DGDNT

Deuteronomy 6 in the DHNT

Deuteronomy 6 in the DNT

Deuteronomy 6 in the ELBE

Deuteronomy 6 in the EMTV

Deuteronomy 6 in the ESV

Deuteronomy 6 in the FBV

Deuteronomy 6 in the FEB

Deuteronomy 6 in the GGMNT

Deuteronomy 6 in the GNT

Deuteronomy 6 in the HARY

Deuteronomy 6 in the HNT

Deuteronomy 6 in the IRVA

Deuteronomy 6 in the IRVB

Deuteronomy 6 in the IRVG

Deuteronomy 6 in the IRVH

Deuteronomy 6 in the IRVK

Deuteronomy 6 in the IRVM

Deuteronomy 6 in the IRVM2

Deuteronomy 6 in the IRVO

Deuteronomy 6 in the IRVP

Deuteronomy 6 in the IRVT

Deuteronomy 6 in the IRVT2

Deuteronomy 6 in the IRVU

Deuteronomy 6 in the ISVN

Deuteronomy 6 in the JSNT

Deuteronomy 6 in the KAPI

Deuteronomy 6 in the KBT1ETNIK

Deuteronomy 6 in the KBV

Deuteronomy 6 in the KJV

Deuteronomy 6 in the KNFD

Deuteronomy 6 in the LBA

Deuteronomy 6 in the LBLA

Deuteronomy 6 in the LNT

Deuteronomy 6 in the LSV

Deuteronomy 6 in the MAAL

Deuteronomy 6 in the MBV

Deuteronomy 6 in the MBV2

Deuteronomy 6 in the MHNT

Deuteronomy 6 in the MKNFD

Deuteronomy 6 in the MNG

Deuteronomy 6 in the MNT

Deuteronomy 6 in the MNT2

Deuteronomy 6 in the MRS1T

Deuteronomy 6 in the NAA

Deuteronomy 6 in the NASB

Deuteronomy 6 in the NBLA

Deuteronomy 6 in the NBS

Deuteronomy 6 in the NBVTP

Deuteronomy 6 in the NET2

Deuteronomy 6 in the NIV11

Deuteronomy 6 in the NNT

Deuteronomy 6 in the NNT2

Deuteronomy 6 in the NNT3

Deuteronomy 6 in the PDDPT

Deuteronomy 6 in the PFNT

Deuteronomy 6 in the RMNT

Deuteronomy 6 in the SBIAS

Deuteronomy 6 in the SBIBS

Deuteronomy 6 in the SBIBS2

Deuteronomy 6 in the SBICS

Deuteronomy 6 in the SBIDS

Deuteronomy 6 in the SBIGS

Deuteronomy 6 in the SBIHS

Deuteronomy 6 in the SBIIS

Deuteronomy 6 in the SBIIS2

Deuteronomy 6 in the SBIIS3

Deuteronomy 6 in the SBIKS

Deuteronomy 6 in the SBIKS2

Deuteronomy 6 in the SBIMS

Deuteronomy 6 in the SBIOS

Deuteronomy 6 in the SBIPS

Deuteronomy 6 in the SBISS

Deuteronomy 6 in the SBITS

Deuteronomy 6 in the SBITS2

Deuteronomy 6 in the SBITS3

Deuteronomy 6 in the SBITS4

Deuteronomy 6 in the SBIUS

Deuteronomy 6 in the SBIVS

Deuteronomy 6 in the SBT

Deuteronomy 6 in the SBT1E

Deuteronomy 6 in the SCHL

Deuteronomy 6 in the SNT

Deuteronomy 6 in the SUSU

Deuteronomy 6 in the SUSU2

Deuteronomy 6 in the SYNO

Deuteronomy 6 in the TBIAOTANT

Deuteronomy 6 in the TBT1E

Deuteronomy 6 in the TBT1E2

Deuteronomy 6 in the TFTIP

Deuteronomy 6 in the TFTU

Deuteronomy 6 in the TGNTATF3T

Deuteronomy 6 in the THAI

Deuteronomy 6 in the TNFD

Deuteronomy 6 in the TNT

Deuteronomy 6 in the TNTIK

Deuteronomy 6 in the TNTIL

Deuteronomy 6 in the TNTIN

Deuteronomy 6 in the TNTIP

Deuteronomy 6 in the TNTIZ

Deuteronomy 6 in the TOMA

Deuteronomy 6 in the TTENT

Deuteronomy 6 in the UBG

Deuteronomy 6 in the UGV

Deuteronomy 6 in the UGV2

Deuteronomy 6 in the UGV3

Deuteronomy 6 in the VBL

Deuteronomy 6 in the VDCC

Deuteronomy 6 in the YALU

Deuteronomy 6 in the YAPE

Deuteronomy 6 in the YBVTP

Deuteronomy 6 in the ZBP