Exodus 2 (BOYCB)

1 Ó sì ṣe, ọkùnrin ará ilé Lefi kan fẹ́ ọmọbìnrin ará Lefi kan ni ìyàwó. 2 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Nígbà tí ó rí í pé ọmọ náà rẹwà, ó gbé ọmọ náà pamọ́ fún oṣù mẹ́ta. 3 Ṣùgbọ́n nígbà tí kò le è gbé e pamọ́ mọ́, ó fi ewé papirusi hun apẹ̀rẹ̀, ó sì fi ọ̀dà àti òjé igi sán apẹ̀rẹ̀ náà. Ó sì tẹ́ ọmọ náà sínú rẹ̀, ó sì gbe é sí inú eèsún ni etí odò Naili. 4 Arábìnrin rẹ̀ dúró ni òkèèrè láti wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọ náà. 5 Nígbà náà ni ọmọbìnrin Farao sọ̀kalẹ̀ wá sí etí odò Naili láti wẹ̀, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sì ń rìn ni etí bèbè odò. Ó sì ri apẹ̀rẹ̀ náà ni àárín eèsún, ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin kan láti lọ gbé e wá, 6 ó ṣí i, ó sì rí ọmọ náà. Ọmọ náà ń sọkún, àánú ọmọ náà sì ṣe é. Ó wí pé, “Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Heberu ni èyí.” 7 Nígbà náà ni arábìnrin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ ọmọbìnrin Farao pé, “Ṣé kí èmi lọ wá ọ̀kan lára àwọn obìnrin Heberu wá fún ọ láti bá ọ tọ́jú ọmọ náà?” 8 Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni; lọ.” Arábìnrin náà sì lọ, ó sì pe ìyá ọmọ náà wá. 9 Ọmọbìnrin Farao sì wí fún un pé, “Gba ọmọ yìí kí o sì tọ́jú rẹ̀ fún mi, èmi yóò san owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ fún ọ.” Ọmọbìnrin náà sì gbé ọmọ náà lọ, ó sì tọ́jú rẹ̀. 10 Nígbà tí ọmọ náà sì dàgbà, ó mú un tọ ọmọbìnrin Farao wá, ó sì di ọmọ rẹ̀. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Mose, ó wí pé, “Nítorí tí mo fà á jáde nínú omi.” 11 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Mose ti dàgbà, ó jáde lọ sí ibi ti àwọn ènìyàn rẹ̀ wà, ó ń wò wọ́n lẹ́nu iṣẹ́ líle wọn, ó ri ará Ejibiti tí ń lu ará Heberu, ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn rẹ̀. 12 Ó wo ìhín, ó wo ọ̀hún, nígbà tí kò rí ẹnìkankan, ni ó bá pa ará Ejibiti náà, ó sì bò ó mọ́ inú iyanrìn. 13 Ní ọjọ́ kejì, ó jáde lọ, ó rí àwọn ará Heberu méjì tí wọ́n ń jà. Ó béèrè lọ́wọ́ èyí tí ó jẹ̀bi pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń lu Heberu arákùnrin rẹ?” 14 Ọkùnrin náà sì dáhùn pé, “Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa? Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti?” Nígbà náà ni ẹ̀rù ba Mose, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni ọ̀ràn yìí ti di mí mọ̀.” 15 Nígbà ti Farao sì gbọ́ nípa èyí, ó wá ọ̀nà láti pa Mose, ṣùgbọ́n Mose sá kúrò ní àrọ́wọ́tó o Farao, ó lọ sí Midiani láti máa gbé, nígbà tí ó dé bẹ̀, ó jókòó ni ẹ̀bá a kànga kan. 16 Ó sì ṣe, àlùfáà Midiani kan ni àwọn ọmọbìnrin méje, wọn sì wá láti pọn omi kún ọpọ́n ìmumi fún ẹran ọ̀sìn baba wọn. 17 Àwọn darandaran kan wá, wọ́n sì lé wọn sẹ́yìn, ṣùgbọ́n Mose dìde láti gbà wọ́n sílẹ̀ àti láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti fún ẹran wọn ní omi. 18 Nígbà ti àwọn ọmọbìnrin náà padà dé ọ̀dọ̀ Reueli baba wọn, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tètè dé ni òní?” 19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ará Ejibiti kan ni ó gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn darandaran, ó tilẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ láti fa omi àti láti fún agbo ẹran ní omi.” 20 Ó sọ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, “Níbo ni ó wà? Èéṣe ti ẹ fi fi ọkùnrin náà sílẹ̀? Ẹ pè é wá jẹun.” 21 Mose gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sippora, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mose láti fi ṣe aya. 22 Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gerṣomu, ó wí pé, “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.” 23 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Ejibiti kú. Àwọn ará Israẹli ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run. 24 Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, Ó sì rántí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti pẹ̀lú Jakọbu. 25 Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Israẹli, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.

In Other Versions

Exodus 2 in the ANGEFD

Exodus 2 in the ANTPNG2D

Exodus 2 in the AS21

Exodus 2 in the BAGH

Exodus 2 in the BBPNG

Exodus 2 in the BBT1E

Exodus 2 in the BDS

Exodus 2 in the BEV

Exodus 2 in the BHAD

Exodus 2 in the BIB

Exodus 2 in the BLPT

Exodus 2 in the BNT

Exodus 2 in the BNTABOOT

Exodus 2 in the BNTLV

Exodus 2 in the BOATCB

Exodus 2 in the BOATCB2

Exodus 2 in the BOBCV

Exodus 2 in the BOCNT

Exodus 2 in the BOECS

Exodus 2 in the BOGWICC

Exodus 2 in the BOHCB

Exodus 2 in the BOHCV

Exodus 2 in the BOHLNT

Exodus 2 in the BOHNTLTAL

Exodus 2 in the BOICB

Exodus 2 in the BOILNTAP

Exodus 2 in the BOITCV

Exodus 2 in the BOKCV

Exodus 2 in the BOKCV2

Exodus 2 in the BOKHWOG

Exodus 2 in the BOKSSV

Exodus 2 in the BOLCB

Exodus 2 in the BOLCB2

Exodus 2 in the BOMCV

Exodus 2 in the BONAV

Exodus 2 in the BONCB

Exodus 2 in the BONLT

Exodus 2 in the BONUT2

Exodus 2 in the BOPLNT

Exodus 2 in the BOSCB

Exodus 2 in the BOSNC

Exodus 2 in the BOTLNT

Exodus 2 in the BOVCB

Exodus 2 in the BPBB

Exodus 2 in the BPH

Exodus 2 in the BSB

Exodus 2 in the CCB

Exodus 2 in the CUV

Exodus 2 in the CUVS

Exodus 2 in the DBT

Exodus 2 in the DGDNT

Exodus 2 in the DHNT

Exodus 2 in the DNT

Exodus 2 in the ELBE

Exodus 2 in the EMTV

Exodus 2 in the ESV

Exodus 2 in the FBV

Exodus 2 in the FEB

Exodus 2 in the GGMNT

Exodus 2 in the GNT

Exodus 2 in the HARY

Exodus 2 in the HNT

Exodus 2 in the IRVA

Exodus 2 in the IRVB

Exodus 2 in the IRVG

Exodus 2 in the IRVH

Exodus 2 in the IRVK

Exodus 2 in the IRVM

Exodus 2 in the IRVM2

Exodus 2 in the IRVO

Exodus 2 in the IRVP

Exodus 2 in the IRVT

Exodus 2 in the IRVT2

Exodus 2 in the IRVU

Exodus 2 in the ISVN

Exodus 2 in the JSNT

Exodus 2 in the KAPI

Exodus 2 in the KBT1ETNIK

Exodus 2 in the KBV

Exodus 2 in the KJV

Exodus 2 in the KNFD

Exodus 2 in the LBA

Exodus 2 in the LBLA

Exodus 2 in the LNT

Exodus 2 in the LSV

Exodus 2 in the MAAL

Exodus 2 in the MBV

Exodus 2 in the MBV2

Exodus 2 in the MHNT

Exodus 2 in the MKNFD

Exodus 2 in the MNG

Exodus 2 in the MNT

Exodus 2 in the MNT2

Exodus 2 in the MRS1T

Exodus 2 in the NAA

Exodus 2 in the NASB

Exodus 2 in the NBLA

Exodus 2 in the NBS

Exodus 2 in the NBVTP

Exodus 2 in the NET2

Exodus 2 in the NIV11

Exodus 2 in the NNT

Exodus 2 in the NNT2

Exodus 2 in the NNT3

Exodus 2 in the PDDPT

Exodus 2 in the PFNT

Exodus 2 in the RMNT

Exodus 2 in the SBIAS

Exodus 2 in the SBIBS

Exodus 2 in the SBIBS2

Exodus 2 in the SBICS

Exodus 2 in the SBIDS

Exodus 2 in the SBIGS

Exodus 2 in the SBIHS

Exodus 2 in the SBIIS

Exodus 2 in the SBIIS2

Exodus 2 in the SBIIS3

Exodus 2 in the SBIKS

Exodus 2 in the SBIKS2

Exodus 2 in the SBIMS

Exodus 2 in the SBIOS

Exodus 2 in the SBIPS

Exodus 2 in the SBISS

Exodus 2 in the SBITS

Exodus 2 in the SBITS2

Exodus 2 in the SBITS3

Exodus 2 in the SBITS4

Exodus 2 in the SBIUS

Exodus 2 in the SBIVS

Exodus 2 in the SBT

Exodus 2 in the SBT1E

Exodus 2 in the SCHL

Exodus 2 in the SNT

Exodus 2 in the SUSU

Exodus 2 in the SUSU2

Exodus 2 in the SYNO

Exodus 2 in the TBIAOTANT

Exodus 2 in the TBT1E

Exodus 2 in the TBT1E2

Exodus 2 in the TFTIP

Exodus 2 in the TFTU

Exodus 2 in the TGNTATF3T

Exodus 2 in the THAI

Exodus 2 in the TNFD

Exodus 2 in the TNT

Exodus 2 in the TNTIK

Exodus 2 in the TNTIL

Exodus 2 in the TNTIN

Exodus 2 in the TNTIP

Exodus 2 in the TNTIZ

Exodus 2 in the TOMA

Exodus 2 in the TTENT

Exodus 2 in the UBG

Exodus 2 in the UGV

Exodus 2 in the UGV2

Exodus 2 in the UGV3

Exodus 2 in the VBL

Exodus 2 in the VDCC

Exodus 2 in the YALU

Exodus 2 in the YAPE

Exodus 2 in the YBVTP

Exodus 2 in the ZBP