Ezekiel 29 (BOYCB)

1 Ní ọjọ́ kejìlá, oṣù kẹwàá, ọdún kẹwàá, ọ̀rọ̀ OLÚWA tọ̀ mí wá wí pé: 2 “Ọmọ ènìyàn, kọjú sí Farao ọba Ejibiti kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí i àti sí gbogbo Ejibiti. 3 Sọ̀rọ̀, kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ní OLÚWA Olódùmarè wí:“ ‘Èmi lòdì sí ọ, Farao ọba Ejibitiìwọ ẹ̀mí búburú ńlá inú òkun tí ó dùbúlẹ̀ síàárín àwọn odò ṣíṣàn rẹ.Èyí tí ó sọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili;èmi ni ó sì ṣe é fún ara mi.” 4 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìwọ̀ mú ẹnu rẹèmi yóò sì mú ẹja inú odò rẹgbogbo lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ.Èmi yóò fà ọ́ síta kúrò láàrín àwọn odò rẹ,àti gbogbo ẹja odò rẹ yóò lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ. 5 Èmi yóò sọ ọ́ nù sí aginjùìwọ àti gbogbo ẹja inú odò rẹ:ìwọ yóò ṣubú sí gbangba okoa kì yóò sì ṣà ọ́ jọ tàbí gbé ọ sókè.Èmi ti fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹranko igbóàti fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run láti jẹ. 6 Nígbà náà gbogbo àwọn olùgbé ni Ejibiti yóò mọ pé, Èmi ni OLÚWA. “ ‘Ìwọ ti jẹ́ ọ̀pá ìyè fún ilé Israẹli. 7 Nígbà tí wọn fi ọwọ́ agbára wọn dì ọ́ mú. Ìwọ fọ́, ìwọ sì ya gbogbo èjìká wọn; nígbà tí wọn fi ara tì ọ́, ìwọ sẹ́, ìwọ sì mú gbogbo ẹ̀gbẹ́ wọn gbọ̀n. 8 “ ‘Nítorí náà, èyí ní OLÚWA Olódùmarè wí: Kíyèsi, Èmi yóò mú idà kan wá sórí rẹ tí yóò sì gé ènìyàn àti ẹran kúrò nínú rẹ. 9 Ilẹ̀ Ejibiti yóò di aginjù àti ahoro, nígbà náà ní wọn yóò sì mọ̀ wí pé èmi ní OLÚWA.“ ‘Nítorí tí ìwọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili, Èmi ni mo ṣe é,” 10 nítorí náà, mo lòdì sí ọ àti sí àwọn odò rẹ, èmi yóò sì mú kí ilẹ̀ Ejibiti di píparun àti ahoro, pátápátá, láti Migdoli lọ dé Siene, dé ààlà ilẹ̀ Kuṣi. 11 Kò sí ẹsẹ̀ ènìyàn tàbí tí ẹranko tí yóò gba ibẹ̀ kọjá; ẹni kankan kò ní gbé ibẹ̀ fún ogójì ọdún. 12 Èmi yóò sọ ilẹ̀ Ejibiti di ọ̀kan ní àárín àwọn ìlú tí ó di ahoro, fún ogójì ọdún, Èmi yóò sì fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sáàárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sáàárín gbogbo ilẹ̀. 13 “ ‘Ṣùgbọ́n báyìí ní OLÚWA Olódùmarè wí: Ní òpin ogójì ọdún, èmi yóò ṣa àwọn ará Ejibiti jọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn níbi tí a fọ́n wọn ká sí. 14 Èmi yóò sì tún mú ìgbèkùn Ejibiti padà bọ̀, èmi yóò sì dá wọn padà sí ilẹ̀ Paturosi, ilẹ̀ àwọn baba ńlá wọn. Wọn yóò wà níbẹ̀ bí ìjọba tí a rẹ̀ sílẹ̀. 15 Ibẹ̀ yóò jẹ́ ìjọba tí ó rẹlẹ̀ jùlọ nínú àwọn ìjọba, kì yóò sì gbé ara rẹ̀ ga mọ́ sórí àwọn orílẹ̀-èdè: nítorí èmi ni ó dín wọn kù, tiwọn kì yóò fi ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù mọ́. 16 Ejibiti kí yóò sì jẹ orísun ìgbẹ́kẹ̀lé fún ilé Israẹli mọ́ ṣùgbọ́n, yóò jẹ́ ìrántí fún àìṣedéédéé wọn, nígbà tí yóò bá wò wọ́n fún ìrànlọ́wọ́. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni OLÚWA Olódùmarè.’ ” 17 Ó sì ṣe ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní, ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n, ọ̀rọ̀ OLÚWA tọ̀ mí wá wí pé: 18 “Ọmọ ènìyàn, Nebukadnessari ọba Babeli mú kí ogun rẹ sin ìrú ńlá fún Tire. Gbogbo orí pá, àti gbogbo èjìká bó, síbẹ̀, òun àti àwọn ogun rẹ̀, kò rí owó ọ̀yà gbà láti Tire fún wa, fún ìrú ti a ti sìn. 19 Nítorí náà, báyìí ni OLÚWA Olódùmarè wí: Kíyèsi i, Èmi yóò fi Ejibiti fún Nebukadnessari ọba Babeli, òun yóò sì kó ọrọ̀ rẹ̀ lọ. Òun yóò bo ilé, yóò sì ṣe ìkógun ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ tí a san fún ológun rẹ̀. 20 Èmi ti fi Ejibiti fún un gẹ́gẹ́ bí èrè wàhálà rẹ̀ nítorí òun àti àwọn ológun rẹ ṣe é fún mi, ni OLÚWA Olódùmarè wí. 21 “Ní ọjọ́ náà, èmi yóò mú kí ìwo Israẹli ru jáde, èmi yóò sì fún ọ ní ẹnu ọ̀rọ̀ ní àárín wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ni OLÚWA.”

In Other Versions

Ezekiel 29 in the ANGEFD

Ezekiel 29 in the ANTPNG2D

Ezekiel 29 in the AS21

Ezekiel 29 in the BAGH

Ezekiel 29 in the BBPNG

Ezekiel 29 in the BBT1E

Ezekiel 29 in the BDS

Ezekiel 29 in the BEV

Ezekiel 29 in the BHAD

Ezekiel 29 in the BIB

Ezekiel 29 in the BLPT

Ezekiel 29 in the BNT

Ezekiel 29 in the BNTABOOT

Ezekiel 29 in the BNTLV

Ezekiel 29 in the BOATCB

Ezekiel 29 in the BOATCB2

Ezekiel 29 in the BOBCV

Ezekiel 29 in the BOCNT

Ezekiel 29 in the BOECS

Ezekiel 29 in the BOGWICC

Ezekiel 29 in the BOHCB

Ezekiel 29 in the BOHCV

Ezekiel 29 in the BOHLNT

Ezekiel 29 in the BOHNTLTAL

Ezekiel 29 in the BOICB

Ezekiel 29 in the BOILNTAP

Ezekiel 29 in the BOITCV

Ezekiel 29 in the BOKCV

Ezekiel 29 in the BOKCV2

Ezekiel 29 in the BOKHWOG

Ezekiel 29 in the BOKSSV

Ezekiel 29 in the BOLCB

Ezekiel 29 in the BOLCB2

Ezekiel 29 in the BOMCV

Ezekiel 29 in the BONAV

Ezekiel 29 in the BONCB

Ezekiel 29 in the BONLT

Ezekiel 29 in the BONUT2

Ezekiel 29 in the BOPLNT

Ezekiel 29 in the BOSCB

Ezekiel 29 in the BOSNC

Ezekiel 29 in the BOTLNT

Ezekiel 29 in the BOVCB

Ezekiel 29 in the BPBB

Ezekiel 29 in the BPH

Ezekiel 29 in the BSB

Ezekiel 29 in the CCB

Ezekiel 29 in the CUV

Ezekiel 29 in the CUVS

Ezekiel 29 in the DBT

Ezekiel 29 in the DGDNT

Ezekiel 29 in the DHNT

Ezekiel 29 in the DNT

Ezekiel 29 in the ELBE

Ezekiel 29 in the EMTV

Ezekiel 29 in the ESV

Ezekiel 29 in the FBV

Ezekiel 29 in the FEB

Ezekiel 29 in the GGMNT

Ezekiel 29 in the GNT

Ezekiel 29 in the HARY

Ezekiel 29 in the HNT

Ezekiel 29 in the IRVA

Ezekiel 29 in the IRVB

Ezekiel 29 in the IRVG

Ezekiel 29 in the IRVH

Ezekiel 29 in the IRVK

Ezekiel 29 in the IRVM

Ezekiel 29 in the IRVM2

Ezekiel 29 in the IRVO

Ezekiel 29 in the IRVP

Ezekiel 29 in the IRVT

Ezekiel 29 in the IRVT2

Ezekiel 29 in the IRVU

Ezekiel 29 in the ISVN

Ezekiel 29 in the JSNT

Ezekiel 29 in the KAPI

Ezekiel 29 in the KBT1ETNIK

Ezekiel 29 in the KBV

Ezekiel 29 in the KJV

Ezekiel 29 in the KNFD

Ezekiel 29 in the LBA

Ezekiel 29 in the LBLA

Ezekiel 29 in the LNT

Ezekiel 29 in the LSV

Ezekiel 29 in the MAAL

Ezekiel 29 in the MBV

Ezekiel 29 in the MBV2

Ezekiel 29 in the MHNT

Ezekiel 29 in the MKNFD

Ezekiel 29 in the MNG

Ezekiel 29 in the MNT

Ezekiel 29 in the MNT2

Ezekiel 29 in the MRS1T

Ezekiel 29 in the NAA

Ezekiel 29 in the NASB

Ezekiel 29 in the NBLA

Ezekiel 29 in the NBS

Ezekiel 29 in the NBVTP

Ezekiel 29 in the NET2

Ezekiel 29 in the NIV11

Ezekiel 29 in the NNT

Ezekiel 29 in the NNT2

Ezekiel 29 in the NNT3

Ezekiel 29 in the PDDPT

Ezekiel 29 in the PFNT

Ezekiel 29 in the RMNT

Ezekiel 29 in the SBIAS

Ezekiel 29 in the SBIBS

Ezekiel 29 in the SBIBS2

Ezekiel 29 in the SBICS

Ezekiel 29 in the SBIDS

Ezekiel 29 in the SBIGS

Ezekiel 29 in the SBIHS

Ezekiel 29 in the SBIIS

Ezekiel 29 in the SBIIS2

Ezekiel 29 in the SBIIS3

Ezekiel 29 in the SBIKS

Ezekiel 29 in the SBIKS2

Ezekiel 29 in the SBIMS

Ezekiel 29 in the SBIOS

Ezekiel 29 in the SBIPS

Ezekiel 29 in the SBISS

Ezekiel 29 in the SBITS

Ezekiel 29 in the SBITS2

Ezekiel 29 in the SBITS3

Ezekiel 29 in the SBITS4

Ezekiel 29 in the SBIUS

Ezekiel 29 in the SBIVS

Ezekiel 29 in the SBT

Ezekiel 29 in the SBT1E

Ezekiel 29 in the SCHL

Ezekiel 29 in the SNT

Ezekiel 29 in the SUSU

Ezekiel 29 in the SUSU2

Ezekiel 29 in the SYNO

Ezekiel 29 in the TBIAOTANT

Ezekiel 29 in the TBT1E

Ezekiel 29 in the TBT1E2

Ezekiel 29 in the TFTIP

Ezekiel 29 in the TFTU

Ezekiel 29 in the TGNTATF3T

Ezekiel 29 in the THAI

Ezekiel 29 in the TNFD

Ezekiel 29 in the TNT

Ezekiel 29 in the TNTIK

Ezekiel 29 in the TNTIL

Ezekiel 29 in the TNTIN

Ezekiel 29 in the TNTIP

Ezekiel 29 in the TNTIZ

Ezekiel 29 in the TOMA

Ezekiel 29 in the TTENT

Ezekiel 29 in the UBG

Ezekiel 29 in the UGV

Ezekiel 29 in the UGV2

Ezekiel 29 in the UGV3

Ezekiel 29 in the VBL

Ezekiel 29 in the VDCC

Ezekiel 29 in the YALU

Ezekiel 29 in the YAPE

Ezekiel 29 in the YBVTP

Ezekiel 29 in the ZBP