Nehemiah 4 (BOYCB)

1 Nígbà tí Sanballati gbọ́ pé àwa ń tún odi náà mọ, ó bínú, ó sì bínú púpọ̀. Ó fi àwọn ará Júù ṣe ẹlẹ́yà, 2 ó sọ níwájú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àti níwájú àwọn ọmọ-ogun Samaria pé, “Kí ni àwọn aláìlera Júù wọ̀nyí ń ṣe yìí? Ṣé wọn yóò mú odi wọn padà ni? Ṣé wọn yóò rú ẹbọ ni? Ṣé wọn yóò parí i rẹ̀ lóòjọ́ ni bí? Ṣé wọ́n lè mú òkúta tí a ti sun láti inú òkìtì padà bọ̀ sípò tí ó jóná bí wọ́n ṣe wà?” 3 Tobiah ará Ammoni, ẹni tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, wí pé, “Ohun tí wọ́n ń mọ—bí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ lásán bá gùn ún sókè, yóò fọ́ odi òkúta wọn lulẹ̀!” 4 Gbọ́ ti wa, Ọlọ́run wa, nítorí àwa di ẹni ẹ̀gàn. Dá ẹ̀gàn wọn padà sórí ara wọn. Kí o sì fi wọ́n fún ìkógun ní ilẹ̀ ìgbèkùn. 5 Má ṣe bo ẹ̀bi wọn tàbí wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn nù kúrò níwájú rẹ, nítorí wọ́n mú ọ bínú níwájú àwọn ọ̀mọ̀lé. 6 Bẹ́ẹ̀ ni àwa mọ odi náà títí gbogbo rẹ̀ fi dé ìdajì gíga rẹ̀, nítorí àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an wọn. 7 Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati, Tobiah, àwọn ará Arabia, ará Ammoni, àti àwọn ènìyàn Aṣdodu gbọ́ pé àtúnṣe odi Jerusalẹmu ti ga dé òkè àti pé a ti mọ àwọn ibi tí ó yá dí, inú bí wọn gidigidi. 8 Gbogbo wọn jọ gbìmọ̀ pọ̀ láti wá bá Jerusalẹmu jà àti láti dìde wàhálà sí í. 9 Ṣùgbọ́n àwa gbàdúrà sí Ọlọ́run wa, a sì yan olùṣọ́ ọ̀sán àti ti òru láti kojú ìhàlẹ̀ yìí. 10 Lákòókò yìí, àwọn ènìyàn Juda wí pé, “Agbára àwọn òṣìṣẹ́ ti dínkù, àlàpà púpọ̀ ni ó wà tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi le è mọ odi náà.” 11 Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ọ̀tá wa wí pé, “Kí wọn tó mọ̀ tàbí kí wọn tó rí wa, àwa yóò ti dé àárín wọn, a ó sì pa wọ́n, a ó sì dá iṣẹ́ náà dúró.” 12 Nígbà náà ni àwọn Júù tí ó ń gbé ní ẹ̀gbẹ́ wọn wá sọ fún wa ní ìgbà mẹ́wàá pé, “Ibikíbi tí ẹ̀yin bá padà sí, wọn yóò kọlù wá.” 13 Nítorí náà mo dá ènìyàn díẹ̀ dúró níbi tí ó rẹlẹ̀ jù lẹ́yìn odi ní ibi gbangba, mo fi wọ́n síbẹ̀ nípa àwọn ìdílé wọn, pẹ̀lú àwọn idà wọn, àwọn ọ̀kọ̀ wọn àti àwọn ọrun wọn. 14 Lẹ́yìn ìgbà tí mo wo àwọn nǹkan yíká, mo dìde mo sì wí fún àwọn ọlọ́lá àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù u wọn. Ẹ rántí OLÚWA, ẹni tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, kí ẹ sì jà fún àwọn arákùnrin yín, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, àwọn ìyàwó yín àti àwọn ilé yín.” 15 Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ pé àwa ti mọ èrò wọn àti wí pé Ọlọ́run ti bà á jẹ́, gbogbo wa padà sí ibi odi, ẹnìkọ̀ọ̀kan sí ibi iṣẹ́ tirẹ̀. 16 Láti ọjọ́ náà lọ, ìdajì àwọn ènìyàn ń ṣe iṣẹ́ náà, nígbà tí àwọn ìdajì tókù múra pẹ̀lú ọ̀kọ̀, asà, ọrun àti ìhámọ́ra. Àwọn ìjòyè sì pín ara wọn sẹ́yìn gbogbo ènìyàn Juda. 17 Àwọn ẹni tí ó ń mọ odi. Àwọn tí ń ru àwọn ohun èlò ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú ọwọ́ kan, wọ́n sì fi ọwọ́ kejì di ohun ìjà mú, 18 olúkúlùkù àwọn ọ̀mọ̀lé fi idà wọn sí ẹ̀gbẹ́ wọn bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́. Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí ń fọn ìpè dúró pẹ̀lú mi. 19 Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Iṣẹ́ náà fẹ̀ ó sì pọ̀, a sì ti jìnnà sí ara wa púpọ̀ lórí odi. 20 Níbikíbi tí ẹ bá ti gbọ́ ohùn ìpè, ẹ da ara pọ̀ mọ́ wa níbẹ̀. Ọlọ́run wa yóò jà fún wa!” 21 Bẹ́ẹ̀ ni àwa ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àwọn ìdajì ènìyàn tí ó di ọ̀kọ̀ mú, láti òwúrọ̀ kùtùkùtù títí di ìgbà tí ìràwọ̀ yóò fi yọ. 22 Ní ìgbà náà mo tún sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn àti olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ dúró ní Jerusalẹmu ní òru, nítorí kí wọn le jẹ́ ẹ̀ṣọ́ fún wa ní òru, kí wọn sì le ṣe iṣẹ́ ní ọ̀sán.” 23 Bẹ́ẹ̀ ni èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi àti àwọn ẹ̀ṣọ́ tí ó wà pẹ̀lú mi kò bọ́ aṣọ wa, olúkúlùkù wa ní ohun ìjà tirẹ̀, kódà nígbà tí wọ́n bá ń lọ pọn omi.

In Other Versions

Nehemiah 4 in the ANGEFD

Nehemiah 4 in the ANTPNG2D

Nehemiah 4 in the AS21

Nehemiah 4 in the BAGH

Nehemiah 4 in the BBPNG

Nehemiah 4 in the BBT1E

Nehemiah 4 in the BDS

Nehemiah 4 in the BEV

Nehemiah 4 in the BHAD

Nehemiah 4 in the BIB

Nehemiah 4 in the BLPT

Nehemiah 4 in the BNT

Nehemiah 4 in the BNTABOOT

Nehemiah 4 in the BNTLV

Nehemiah 4 in the BOATCB

Nehemiah 4 in the BOATCB2

Nehemiah 4 in the BOBCV

Nehemiah 4 in the BOCNT

Nehemiah 4 in the BOECS

Nehemiah 4 in the BOGWICC

Nehemiah 4 in the BOHCB

Nehemiah 4 in the BOHCV

Nehemiah 4 in the BOHLNT

Nehemiah 4 in the BOHNTLTAL

Nehemiah 4 in the BOICB

Nehemiah 4 in the BOILNTAP

Nehemiah 4 in the BOITCV

Nehemiah 4 in the BOKCV

Nehemiah 4 in the BOKCV2

Nehemiah 4 in the BOKHWOG

Nehemiah 4 in the BOKSSV

Nehemiah 4 in the BOLCB

Nehemiah 4 in the BOLCB2

Nehemiah 4 in the BOMCV

Nehemiah 4 in the BONAV

Nehemiah 4 in the BONCB

Nehemiah 4 in the BONLT

Nehemiah 4 in the BONUT2

Nehemiah 4 in the BOPLNT

Nehemiah 4 in the BOSCB

Nehemiah 4 in the BOSNC

Nehemiah 4 in the BOTLNT

Nehemiah 4 in the BOVCB

Nehemiah 4 in the BPBB

Nehemiah 4 in the BPH

Nehemiah 4 in the BSB

Nehemiah 4 in the CCB

Nehemiah 4 in the CUV

Nehemiah 4 in the CUVS

Nehemiah 4 in the DBT

Nehemiah 4 in the DGDNT

Nehemiah 4 in the DHNT

Nehemiah 4 in the DNT

Nehemiah 4 in the ELBE

Nehemiah 4 in the EMTV

Nehemiah 4 in the ESV

Nehemiah 4 in the FBV

Nehemiah 4 in the FEB

Nehemiah 4 in the GGMNT

Nehemiah 4 in the GNT

Nehemiah 4 in the HARY

Nehemiah 4 in the HNT

Nehemiah 4 in the IRVA

Nehemiah 4 in the IRVB

Nehemiah 4 in the IRVG

Nehemiah 4 in the IRVH

Nehemiah 4 in the IRVK

Nehemiah 4 in the IRVM

Nehemiah 4 in the IRVM2

Nehemiah 4 in the IRVO

Nehemiah 4 in the IRVP

Nehemiah 4 in the IRVT

Nehemiah 4 in the IRVT2

Nehemiah 4 in the IRVU

Nehemiah 4 in the ISVN

Nehemiah 4 in the JSNT

Nehemiah 4 in the KAPI

Nehemiah 4 in the KBT1ETNIK

Nehemiah 4 in the KBV

Nehemiah 4 in the KJV

Nehemiah 4 in the KNFD

Nehemiah 4 in the LBA

Nehemiah 4 in the LBLA

Nehemiah 4 in the LNT

Nehemiah 4 in the LSV

Nehemiah 4 in the MAAL

Nehemiah 4 in the MBV

Nehemiah 4 in the MBV2

Nehemiah 4 in the MHNT

Nehemiah 4 in the MKNFD

Nehemiah 4 in the MNG

Nehemiah 4 in the MNT

Nehemiah 4 in the MNT2

Nehemiah 4 in the MRS1T

Nehemiah 4 in the NAA

Nehemiah 4 in the NASB

Nehemiah 4 in the NBLA

Nehemiah 4 in the NBS

Nehemiah 4 in the NBVTP

Nehemiah 4 in the NET2

Nehemiah 4 in the NIV11

Nehemiah 4 in the NNT

Nehemiah 4 in the NNT2

Nehemiah 4 in the NNT3

Nehemiah 4 in the PDDPT

Nehemiah 4 in the PFNT

Nehemiah 4 in the RMNT

Nehemiah 4 in the SBIAS

Nehemiah 4 in the SBIBS

Nehemiah 4 in the SBIBS2

Nehemiah 4 in the SBICS

Nehemiah 4 in the SBIDS

Nehemiah 4 in the SBIGS

Nehemiah 4 in the SBIHS

Nehemiah 4 in the SBIIS

Nehemiah 4 in the SBIIS2

Nehemiah 4 in the SBIIS3

Nehemiah 4 in the SBIKS

Nehemiah 4 in the SBIKS2

Nehemiah 4 in the SBIMS

Nehemiah 4 in the SBIOS

Nehemiah 4 in the SBIPS

Nehemiah 4 in the SBISS

Nehemiah 4 in the SBITS

Nehemiah 4 in the SBITS2

Nehemiah 4 in the SBITS3

Nehemiah 4 in the SBITS4

Nehemiah 4 in the SBIUS

Nehemiah 4 in the SBIVS

Nehemiah 4 in the SBT

Nehemiah 4 in the SBT1E

Nehemiah 4 in the SCHL

Nehemiah 4 in the SNT

Nehemiah 4 in the SUSU

Nehemiah 4 in the SUSU2

Nehemiah 4 in the SYNO

Nehemiah 4 in the TBIAOTANT

Nehemiah 4 in the TBT1E

Nehemiah 4 in the TBT1E2

Nehemiah 4 in the TFTIP

Nehemiah 4 in the TFTU

Nehemiah 4 in the TGNTATF3T

Nehemiah 4 in the THAI

Nehemiah 4 in the TNFD

Nehemiah 4 in the TNT

Nehemiah 4 in the TNTIK

Nehemiah 4 in the TNTIL

Nehemiah 4 in the TNTIN

Nehemiah 4 in the TNTIP

Nehemiah 4 in the TNTIZ

Nehemiah 4 in the TOMA

Nehemiah 4 in the TTENT

Nehemiah 4 in the UBG

Nehemiah 4 in the UGV

Nehemiah 4 in the UGV2

Nehemiah 4 in the UGV3

Nehemiah 4 in the VBL

Nehemiah 4 in the VDCC

Nehemiah 4 in the YALU

Nehemiah 4 in the YAPE

Nehemiah 4 in the YBVTP

Nehemiah 4 in the ZBP