Revelation 14 (BOYCB)

1 Mo sì wo, si kíyèsi i, Ọ̀dọ́-Àgùntàn náà dúró lórí òkè Sioni, àti pẹ̀lú rẹ̀ ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì (144,000) ènìyàn; wọ́n ní orúkọ rẹ̀, àti orúkọ baba rẹ̀ tí a kọ sí iwájú orí wọn. 2 Mo sì gbọ́ ohùn kan láti ọ̀run wá, bí ariwo omi púpọ̀, àti bí sísán àrá ńlá, mo sì gbọ́ àwọn aludùùrù tí wọn ń lu dùùrù. 3 Wọ́n sì ń kọ bí ẹni pé orin tuntun níwájú ìtẹ́ náà, àti níwájú àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin n nì àti àwọn àgbà náà, kò sì ṣí ẹni tí o lè kọ orin náà, bí kò ṣe àwọn ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì (144,000) ènìyàn, tí a tí rà padà láti inú ayé wá. 4 Àwọn wọ̀nyí ni a kò fi obìnrin sọ di èérí, nítorí tí wọ́n jẹ́ wúńdíá. Àwọn wọ̀nyí ni o ń tọ Ọ̀dọ́-àgùntàn náà lẹ́yìn níbikíbi tí o bá ń lọ. Àwọn wọ̀nyí ni a rà padà láti inú àwọn ènìyàn wá, wọ́n jẹ́ àkọ́so fún Ọlọ́run àti fún Ọ̀dọ́-Àgùntàn náà. 5 A kò sì rí èké lẹ́nu wọn, wọn jẹ́ aláìlábùkù. 6 Mo sì rí angẹli mìíràn ń fò ní àárín méjì ọ̀run, pẹ̀lú ìyìnrere àìnípẹ̀kun láti wàásù fún àwọn tí ń gbé orí ilẹ̀ ayé, àti fún gbogbo orílẹ̀, àti ẹ̀yà, àti èdè, àti ènìyàn. 7 Ó ń wí ni ohùn rara pé, “Ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run, kí ẹ sì fi ògo fún un, nítorí tí wákàtí ìdájọ́ rẹ̀ dé: ẹ sì foríbalẹ̀ fún ẹni tí o dá ọ̀run, àti ayé, àti Òkun, àti àwọn orísun omi!” 8 Angẹli mìíràn sì tẹ̀lé e, ó ń wí pé, “o ṣubú, Babeli ńlá ṣubú, èyí ti o tí ń mú gbogbo orílẹ̀-èdè mu nínú ọtí wáìnì àìmọ́ àgbèrè rẹ̀!” 9 Angẹli mìíràn, ẹ̀kẹta, sì tẹ̀lé wọn, ó ń wí ni ohùn rara pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá ń foríbalẹ̀ fún ẹranko náà àti àwòrán rẹ̀, tí ó sì gba àmì sí iwájú orí rẹ̀ tàbí sí ọwọ́ rẹ̀. 10 Òun pẹ̀lú yóò mú nínú ọtí wáìnì ìbínú Ọlọ́run, tí a dà ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ sínú ago ìrunú rẹ̀; a ó sì fi iná sulfuru dá a lóró níwájú àwọn angẹli mímọ́, àti níwájú Ọ̀dọ́-àgùntàn. 11 Èéfín ìdálóró wọn ń lọ sókè títí láéláé wọn kò sì ní ìsinmi ni ọ̀sán àti ní òru, àwọn tí ń foríbalẹ̀ fún ẹranko náà àti fún àwòrán rẹ̀, àti ẹnikẹ́ni tí o ba sì gba àmì orúkọ rẹ̀.” 12 Níhìn-ín ni sùúrù àwọn ènìyàn mímọ́ gbé wà: àwọn tí ń pa òfin Ọlọ́run àti ìgbàgbọ́ Jesu mọ́. 13 Mo sì gbọ́ ohùn kan láti ọ̀run wá ń wí fún mi pé, “Kọ̀wé rẹ̀, Alábùkún fún ni àwọn òkú tí o kú nínú Olúwa láti ìhín lọ.”Alábùkún ni wọ́n nítòótọ́, bẹ́ẹ̀ ni, Ẹ̀mí wí, “Nítorí tí wọn yóò sinmi kúrò nínú làálàá wọn, nítorí iṣẹ́ wọn ń tọ̀ wọn lẹ́yìn.” 14 Mo sì wo, sì kíyèsi i, ìkùùkuu àwọsánmọ̀ funfun kan, àti lórí ìkùùkuu àwọsánmọ̀ náà ẹnìkan jókòó tí o dàbí “ọmọ ènìyàn,” tí òun ti adé wúrà ní orí rẹ̀, àti dòjé mímú ni ọwọ́ rẹ̀. 15 Angẹli mìíràn sì tí inú tẹmpili jáde wa tí ń ké lóhùn rara sí ẹni tí ó jókòó lórí ìkùùkuu àwọsánmọ̀ náà pé, “Tẹ dòjé rẹ bọ̀ ọ́, kí ó sì máa kórè; nítorí àkókò àti kórè dé, nítorí ìkórè ayé ti gbó tán.” 16 Ẹni tí ó jókòó lórí ìkùùkuu àwọsánmọ̀ náà sì tẹ dòjé rẹ̀ bọ orí ilẹ̀ ayé; a sì ṣe ìkórè ilẹ̀ ayé. 17 Angẹli mìíràn sì tí inú tẹmpili tí ń bẹ ni ọ̀run jáde wá, òun pẹ̀lú sì ní dòjé mímú, kan. 18 Angẹli mìíràn sì tí ibi pẹpẹ jáde wá, tí ó ní agbára lórí iná; ó sì ké ni ohùn rara sí ẹni tí o ni dòjé mímú náà, wí pé, “Tẹ dòjé rẹ mímú bọ̀ ọ́, ki ó sì rẹ́ àwọn ìdì àjàrà ayé, nítorí àwọn èso rẹ̀ tí pọ́n.” 19 Angẹli náà sì tẹ dòjé rẹ̀ bọ ilẹ̀ ayé, ó sì gé àjàrà ilẹ̀ ayé, ó sì kó o lọ sínú ìfúntí, ìfúntí ńlá ìbínú Ọlọ́run. 20 A sì tẹ ìfúntí náà lẹ́yìn òde ìlú náà, ẹ̀jẹ̀ sì ti inú ìfúntí náà jáde, ó sì ga sókè dé okùn ìjánu ẹṣin, èyí tí ìnàsílẹ̀ rẹ to ẹ̀gbẹjọ̀ (1,600) ibùsọ̀.

In Other Versions

Revelation 14 in the ANGEFD

Revelation 14 in the ANTPNG2D

Revelation 14 in the AS21

Revelation 14 in the BAGH

Revelation 14 in the BBPNG

Revelation 14 in the BBT1E

Revelation 14 in the BDS

Revelation 14 in the BEV

Revelation 14 in the BHAD

Revelation 14 in the BIB

Revelation 14 in the BLPT

Revelation 14 in the BNT

Revelation 14 in the BNTABOOT

Revelation 14 in the BNTLV

Revelation 14 in the BOATCB

Revelation 14 in the BOATCB2

Revelation 14 in the BOBCV

Revelation 14 in the BOCNT

Revelation 14 in the BOECS

Revelation 14 in the BOGWICC

Revelation 14 in the BOHCB

Revelation 14 in the BOHCV

Revelation 14 in the BOHLNT

Revelation 14 in the BOHNTLTAL

Revelation 14 in the BOICB

Revelation 14 in the BOILNTAP

Revelation 14 in the BOITCV

Revelation 14 in the BOKCV

Revelation 14 in the BOKCV2

Revelation 14 in the BOKHWOG

Revelation 14 in the BOKSSV

Revelation 14 in the BOLCB

Revelation 14 in the BOLCB2

Revelation 14 in the BOMCV

Revelation 14 in the BONAV

Revelation 14 in the BONCB

Revelation 14 in the BONLT

Revelation 14 in the BONUT2

Revelation 14 in the BOPLNT

Revelation 14 in the BOSCB

Revelation 14 in the BOSNC

Revelation 14 in the BOTLNT

Revelation 14 in the BOVCB

Revelation 14 in the BPBB

Revelation 14 in the BPH

Revelation 14 in the BSB

Revelation 14 in the CCB

Revelation 14 in the CUV

Revelation 14 in the CUVS

Revelation 14 in the DBT

Revelation 14 in the DGDNT

Revelation 14 in the DHNT

Revelation 14 in the DNT

Revelation 14 in the ELBE

Revelation 14 in the EMTV

Revelation 14 in the ESV

Revelation 14 in the FBV

Revelation 14 in the FEB

Revelation 14 in the GGMNT

Revelation 14 in the GNT

Revelation 14 in the HARY

Revelation 14 in the HNT

Revelation 14 in the IRVA

Revelation 14 in the IRVB

Revelation 14 in the IRVG

Revelation 14 in the IRVH

Revelation 14 in the IRVK

Revelation 14 in the IRVM

Revelation 14 in the IRVM2

Revelation 14 in the IRVO

Revelation 14 in the IRVP

Revelation 14 in the IRVT

Revelation 14 in the IRVT2

Revelation 14 in the IRVU

Revelation 14 in the ISVN

Revelation 14 in the JSNT

Revelation 14 in the KAPI

Revelation 14 in the KBT1ETNIK

Revelation 14 in the KBV

Revelation 14 in the KJV

Revelation 14 in the KNFD

Revelation 14 in the LBA

Revelation 14 in the LBLA

Revelation 14 in the LNT

Revelation 14 in the LSV

Revelation 14 in the MAAL

Revelation 14 in the MBV

Revelation 14 in the MBV2

Revelation 14 in the MHNT

Revelation 14 in the MKNFD

Revelation 14 in the MNG

Revelation 14 in the MNT

Revelation 14 in the MNT2

Revelation 14 in the MRS1T

Revelation 14 in the NAA

Revelation 14 in the NASB

Revelation 14 in the NBLA

Revelation 14 in the NBS

Revelation 14 in the NBVTP

Revelation 14 in the NET2

Revelation 14 in the NIV11

Revelation 14 in the NNT

Revelation 14 in the NNT2

Revelation 14 in the NNT3

Revelation 14 in the PDDPT

Revelation 14 in the PFNT

Revelation 14 in the RMNT

Revelation 14 in the SBIAS

Revelation 14 in the SBIBS

Revelation 14 in the SBIBS2

Revelation 14 in the SBICS

Revelation 14 in the SBIDS

Revelation 14 in the SBIGS

Revelation 14 in the SBIHS

Revelation 14 in the SBIIS

Revelation 14 in the SBIIS2

Revelation 14 in the SBIIS3

Revelation 14 in the SBIKS

Revelation 14 in the SBIKS2

Revelation 14 in the SBIMS

Revelation 14 in the SBIOS

Revelation 14 in the SBIPS

Revelation 14 in the SBISS

Revelation 14 in the SBITS

Revelation 14 in the SBITS2

Revelation 14 in the SBITS3

Revelation 14 in the SBITS4

Revelation 14 in the SBIUS

Revelation 14 in the SBIVS

Revelation 14 in the SBT

Revelation 14 in the SBT1E

Revelation 14 in the SCHL

Revelation 14 in the SNT

Revelation 14 in the SUSU

Revelation 14 in the SUSU2

Revelation 14 in the SYNO

Revelation 14 in the TBIAOTANT

Revelation 14 in the TBT1E

Revelation 14 in the TBT1E2

Revelation 14 in the TFTIP

Revelation 14 in the TFTU

Revelation 14 in the TGNTATF3T

Revelation 14 in the THAI

Revelation 14 in the TNFD

Revelation 14 in the TNT

Revelation 14 in the TNTIK

Revelation 14 in the TNTIL

Revelation 14 in the TNTIN

Revelation 14 in the TNTIP

Revelation 14 in the TNTIZ

Revelation 14 in the TOMA

Revelation 14 in the TTENT

Revelation 14 in the UBG

Revelation 14 in the UGV

Revelation 14 in the UGV2

Revelation 14 in the UGV3

Revelation 14 in the VBL

Revelation 14 in the VDCC

Revelation 14 in the YALU

Revelation 14 in the YAPE

Revelation 14 in the YBVTP

Revelation 14 in the ZBP