Jeremiah 16 (BOYCB)

1 Bákan náà ni ọ̀rọ̀ OLÚWA tọ̀ mí wá wí pé: 2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.” 3 Nítorí èyí ni ohun tí OLÚWA wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn. 4 “Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.” 5 Nítorí báyìí ni OLÚWA wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni OLÚWA wí. 6 “Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn. 7 Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú. 8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu. 9 Báyìí ni OLÚWA àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí. 10 “Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí OLÚWA ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí OLÚWA Ọlọ́run wa?’ 11 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni OLÚWA wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́. 12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi. 13 Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’ 14 “Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni OLÚWA wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú OLÚWA wà láààyè OLÚWA ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’ 15 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí OLÚWA ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn. 16 “Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni OLÚWA wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta. 17 Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi. 18 Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.” 19 OLÚWA, alágbára àti okun mi,ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú,àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá látiòpin ayé wí pé,“Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà,ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀. 20 Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́runfún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni,ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.” 21 “Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọnní àkókò yìí,Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi.Nígbà náà ni wọn ó mọpé orúkọ miní OLÚWA.

In Other Versions

Jeremiah 16 in the ANGEFD

Jeremiah 16 in the ANTPNG2D

Jeremiah 16 in the AS21

Jeremiah 16 in the BAGH

Jeremiah 16 in the BBPNG

Jeremiah 16 in the BBT1E

Jeremiah 16 in the BDS

Jeremiah 16 in the BEV

Jeremiah 16 in the BHAD

Jeremiah 16 in the BIB

Jeremiah 16 in the BLPT

Jeremiah 16 in the BNT

Jeremiah 16 in the BNTABOOT

Jeremiah 16 in the BNTLV

Jeremiah 16 in the BOATCB

Jeremiah 16 in the BOATCB2

Jeremiah 16 in the BOBCV

Jeremiah 16 in the BOCNT

Jeremiah 16 in the BOECS

Jeremiah 16 in the BOGWICC

Jeremiah 16 in the BOHCB

Jeremiah 16 in the BOHCV

Jeremiah 16 in the BOHLNT

Jeremiah 16 in the BOHNTLTAL

Jeremiah 16 in the BOICB

Jeremiah 16 in the BOILNTAP

Jeremiah 16 in the BOITCV

Jeremiah 16 in the BOKCV

Jeremiah 16 in the BOKCV2

Jeremiah 16 in the BOKHWOG

Jeremiah 16 in the BOKSSV

Jeremiah 16 in the BOLCB

Jeremiah 16 in the BOLCB2

Jeremiah 16 in the BOMCV

Jeremiah 16 in the BONAV

Jeremiah 16 in the BONCB

Jeremiah 16 in the BONLT

Jeremiah 16 in the BONUT2

Jeremiah 16 in the BOPLNT

Jeremiah 16 in the BOSCB

Jeremiah 16 in the BOSNC

Jeremiah 16 in the BOTLNT

Jeremiah 16 in the BOVCB

Jeremiah 16 in the BPBB

Jeremiah 16 in the BPH

Jeremiah 16 in the BSB

Jeremiah 16 in the CCB

Jeremiah 16 in the CUV

Jeremiah 16 in the CUVS

Jeremiah 16 in the DBT

Jeremiah 16 in the DGDNT

Jeremiah 16 in the DHNT

Jeremiah 16 in the DNT

Jeremiah 16 in the ELBE

Jeremiah 16 in the EMTV

Jeremiah 16 in the ESV

Jeremiah 16 in the FBV

Jeremiah 16 in the FEB

Jeremiah 16 in the GGMNT

Jeremiah 16 in the GNT

Jeremiah 16 in the HARY

Jeremiah 16 in the HNT

Jeremiah 16 in the IRVA

Jeremiah 16 in the IRVB

Jeremiah 16 in the IRVG

Jeremiah 16 in the IRVH

Jeremiah 16 in the IRVK

Jeremiah 16 in the IRVM

Jeremiah 16 in the IRVM2

Jeremiah 16 in the IRVO

Jeremiah 16 in the IRVP

Jeremiah 16 in the IRVT

Jeremiah 16 in the IRVT2

Jeremiah 16 in the IRVU

Jeremiah 16 in the ISVN

Jeremiah 16 in the JSNT

Jeremiah 16 in the KAPI

Jeremiah 16 in the KBT1ETNIK

Jeremiah 16 in the KBV

Jeremiah 16 in the KJV

Jeremiah 16 in the KNFD

Jeremiah 16 in the LBA

Jeremiah 16 in the LBLA

Jeremiah 16 in the LNT

Jeremiah 16 in the LSV

Jeremiah 16 in the MAAL

Jeremiah 16 in the MBV

Jeremiah 16 in the MBV2

Jeremiah 16 in the MHNT

Jeremiah 16 in the MKNFD

Jeremiah 16 in the MNG

Jeremiah 16 in the MNT

Jeremiah 16 in the MNT2

Jeremiah 16 in the MRS1T

Jeremiah 16 in the NAA

Jeremiah 16 in the NASB

Jeremiah 16 in the NBLA

Jeremiah 16 in the NBS

Jeremiah 16 in the NBVTP

Jeremiah 16 in the NET2

Jeremiah 16 in the NIV11

Jeremiah 16 in the NNT

Jeremiah 16 in the NNT2

Jeremiah 16 in the NNT3

Jeremiah 16 in the PDDPT

Jeremiah 16 in the PFNT

Jeremiah 16 in the RMNT

Jeremiah 16 in the SBIAS

Jeremiah 16 in the SBIBS

Jeremiah 16 in the SBIBS2

Jeremiah 16 in the SBICS

Jeremiah 16 in the SBIDS

Jeremiah 16 in the SBIGS

Jeremiah 16 in the SBIHS

Jeremiah 16 in the SBIIS

Jeremiah 16 in the SBIIS2

Jeremiah 16 in the SBIIS3

Jeremiah 16 in the SBIKS

Jeremiah 16 in the SBIKS2

Jeremiah 16 in the SBIMS

Jeremiah 16 in the SBIOS

Jeremiah 16 in the SBIPS

Jeremiah 16 in the SBISS

Jeremiah 16 in the SBITS

Jeremiah 16 in the SBITS2

Jeremiah 16 in the SBITS3

Jeremiah 16 in the SBITS4

Jeremiah 16 in the SBIUS

Jeremiah 16 in the SBIVS

Jeremiah 16 in the SBT

Jeremiah 16 in the SBT1E

Jeremiah 16 in the SCHL

Jeremiah 16 in the SNT

Jeremiah 16 in the SUSU

Jeremiah 16 in the SUSU2

Jeremiah 16 in the SYNO

Jeremiah 16 in the TBIAOTANT

Jeremiah 16 in the TBT1E

Jeremiah 16 in the TBT1E2

Jeremiah 16 in the TFTIP

Jeremiah 16 in the TFTU

Jeremiah 16 in the TGNTATF3T

Jeremiah 16 in the THAI

Jeremiah 16 in the TNFD

Jeremiah 16 in the TNT

Jeremiah 16 in the TNTIK

Jeremiah 16 in the TNTIL

Jeremiah 16 in the TNTIN

Jeremiah 16 in the TNTIP

Jeremiah 16 in the TNTIZ

Jeremiah 16 in the TOMA

Jeremiah 16 in the TTENT

Jeremiah 16 in the UBG

Jeremiah 16 in the UGV

Jeremiah 16 in the UGV2

Jeremiah 16 in the UGV3

Jeremiah 16 in the VBL

Jeremiah 16 in the VDCC

Jeremiah 16 in the YALU

Jeremiah 16 in the YAPE

Jeremiah 16 in the YBVTP

Jeremiah 16 in the ZBP