Nehemiah 5 (BOYCB)

1 Nísinsin yìí àwọn ènìyàn àti àwọn ìyàwó wọn kígbe ńlá sókè sí àwọn Júù arákùnrin wọn. 2 Àwọn kan ń wí pé, “Àwa àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa pọ̀; kí àwa kí ó le è jẹ, kí a sì wà láààyè, a gbọdọ̀ rí oúnjẹ.” 3 Àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ti fi oko wa ọgbà àjàrà wa àti ilé wa dógò kí àwa kí ó lè rí oúnjẹ ní àkókò ìyàn.” 4 Síbẹ̀ àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ní láti yá owó láti san ìṣákọ́lẹ̀ fún ọba lórí àwọn oko wa àti àwọn ọgbà àjàrà wa. 5 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a jẹ́ ẹran-ara kan àti ẹ̀jẹ̀ kan gẹ́gẹ́ bí àwọn ará ìlú wa tí àwọn ọmọkùnrin wa sì dára bí í tiwọn, síbẹ̀ àwa ní láti fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa sí oko ẹrú. Díẹ̀ nínú àwọn ọmọbìnrin wa ti wà lóko ẹrú náà, ṣùgbọ́n àwa kò ní agbára, nítorí àwọn oko àti ọgbà àjàrà wa ti di ti ẹlòmíràn.” 6 Èmi bínú gidigidi nígbà tí mo gbọ́ igbe wọn àti àwọn ẹ̀sùn wọ̀nyí. 7 Mo rò wọ́n wò ní ọkàn mi mo sì fi ẹ̀sùn kan ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè. Mo sọ fún wọn pé, ẹ̀yin ń gba owó èlé lọ́wọ́ àwọn ará ìlú u yín! Nítorí náà mo pe àpéjọ ńlá láti bá wọn wí. 8 Mo sì wí fún wọn pé, “Níbi tí àwa ní agbára mọ, àwa ti ra àwọn Júù arákùnrin wa tí a ti tà fún àwọn tí kì í ṣe Júù padà. Nísinsin yìí ẹ̀yìn ń ta àwọn arákùnrin yín, tí àwa sì tún ní láti rà wọ́n padà!” Wọ́n dákẹ́, nítorí wọn kò rí ohunkóhun sọ. 9 Nítorí náà, mo tẹ̀síwájú pé, “Ohun tí ẹ̀ ń ṣe kò dára. Kò ha yẹ kí ẹ máa rìn nínú ìbẹ̀rù Ọlọ́run bí, láti yẹra fún ẹ̀gàn àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn tí í ṣe ọ̀tá wa? 10 Èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi, pẹ̀lú ń yá àwọn ènìyàn lówó àti oúnjẹ. Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí a dáwọ́ owó èlé gbígbà yìí dúró! 11 Ẹ fún wọn ní oko wọn, ọgbà àjàrà wọn, ọgbà olifi wọn àti ilé e wọn pẹ̀lú owó èlé tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn ìdá ọgọ́rùn-ún owó, oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn padà kíákíá.” 12 Wọ́n wí pé, “Àwa yóò dá a padà. Àwa kì yóò sì béèrè ohunkóhun lọ́wọ́ wọn mọ́. Àwa yóò ṣe bí o ti wí.”Nígbà náà mo pe àwọn àlùfáà, mo sì mú kí àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè búra láti jẹ́ kí wọ́n ṣe ohun tí wọ́n ti ṣe ìlérí. 13 Mo sì gbọn ìṣẹ́tí aṣọ mi, mo wí pé, “Báyìí ni kí Ọlọ́run gbọn olúkúlùkù ènìyàn tí kò bá pa ìlérí yìí mọ́ jáde kúrò ní ilẹ̀ ìní i rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni kí a gbọn irú ẹni bẹ́ẹ̀ jáde kí ó sì ṣófo!”Gbogbo ìjọ ènìyàn sì wí pé, “Àmín,” wọ́n sì fi ìyìn fún OLÚWA. Àwọn ènìyàn náà sì ṣe bí wọ́n ti ṣe ìlérí. 14 Síwájú sí í, láti ogún ọdún ọba Artasasta, nígbà tí a ti yàn mí láti jẹ́ baálẹ̀ wọn ní ilẹ̀ Juda, títí di ọdún kejìlélọ́gbọ̀n ìjọba rẹ̀—ọdún méjìlá, èmi àti àwọn arákùnrin mi kò jẹ oúnjẹ baálẹ̀. 15 Ṣùgbọ́n àwọn baálẹ̀ ìṣáájú—tí ó ti wà ṣáájú mi—gbe àjàgà wúwo lé àwọn ènìyàn lórí yàtọ̀ fún oúnjẹ àti wáìnì wọ́n sì tún gba ogójì ṣékélì fàdákà lọ́wọ́ wọn. Kódà àwọn ìránṣẹ́ wọn tún jẹ gàba lórí wọn. Ṣùgbọ́n èmi kò ṣe bẹ́ẹ̀ nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run. 16 Dípò bẹ́ẹ̀, mo fi ara mi jì fún iṣẹ́ lórí odi yìí. Gbogbo àwọn ènìyàn mi péjọ síbẹ̀ fún iṣẹ́ náà; a kò sì gba ilẹ̀ kankan. 17 Síwájú sí í, àádọ́jọ àwọn Júù àti àwọn ìjòyè jẹun lórí tábìlì mi, àti pẹ̀lú àwọn tí wọ́n wá bá wa láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká. 18 Ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ni a máa ń pèsè màlúù kan, ààyò àgùntàn mẹ́fà àti adìyẹ fún mi àti lẹ́ẹ̀kan ní ọjọ́ mẹ́wàá ni wọ́n máa ń pèsè onírúurú wáìnì tí ó pọ̀ fún mi. Fún gbogbo èyí, èmi kò béèrè oúnjẹ baálẹ̀, nítorí ohun ti a ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí pọ̀ jọjọ. 19 Rántí mi, Ọlọ́run mi, fún rere, nítorí fún gbogbo ohun tí mo ti ṣe fún àwọn ènìyàn yìí.

In Other Versions

Nehemiah 5 in the ANGEFD

Nehemiah 5 in the ANTPNG2D

Nehemiah 5 in the AS21

Nehemiah 5 in the BAGH

Nehemiah 5 in the BBPNG

Nehemiah 5 in the BBT1E

Nehemiah 5 in the BDS

Nehemiah 5 in the BEV

Nehemiah 5 in the BHAD

Nehemiah 5 in the BIB

Nehemiah 5 in the BLPT

Nehemiah 5 in the BNT

Nehemiah 5 in the BNTABOOT

Nehemiah 5 in the BNTLV

Nehemiah 5 in the BOATCB

Nehemiah 5 in the BOATCB2

Nehemiah 5 in the BOBCV

Nehemiah 5 in the BOCNT

Nehemiah 5 in the BOECS

Nehemiah 5 in the BOGWICC

Nehemiah 5 in the BOHCB

Nehemiah 5 in the BOHCV

Nehemiah 5 in the BOHLNT

Nehemiah 5 in the BOHNTLTAL

Nehemiah 5 in the BOICB

Nehemiah 5 in the BOILNTAP

Nehemiah 5 in the BOITCV

Nehemiah 5 in the BOKCV

Nehemiah 5 in the BOKCV2

Nehemiah 5 in the BOKHWOG

Nehemiah 5 in the BOKSSV

Nehemiah 5 in the BOLCB

Nehemiah 5 in the BOLCB2

Nehemiah 5 in the BOMCV

Nehemiah 5 in the BONAV

Nehemiah 5 in the BONCB

Nehemiah 5 in the BONLT

Nehemiah 5 in the BONUT2

Nehemiah 5 in the BOPLNT

Nehemiah 5 in the BOSCB

Nehemiah 5 in the BOSNC

Nehemiah 5 in the BOTLNT

Nehemiah 5 in the BOVCB

Nehemiah 5 in the BPBB

Nehemiah 5 in the BPH

Nehemiah 5 in the BSB

Nehemiah 5 in the CCB

Nehemiah 5 in the CUV

Nehemiah 5 in the CUVS

Nehemiah 5 in the DBT

Nehemiah 5 in the DGDNT

Nehemiah 5 in the DHNT

Nehemiah 5 in the DNT

Nehemiah 5 in the ELBE

Nehemiah 5 in the EMTV

Nehemiah 5 in the ESV

Nehemiah 5 in the FBV

Nehemiah 5 in the FEB

Nehemiah 5 in the GGMNT

Nehemiah 5 in the GNT

Nehemiah 5 in the HARY

Nehemiah 5 in the HNT

Nehemiah 5 in the IRVA

Nehemiah 5 in the IRVB

Nehemiah 5 in the IRVG

Nehemiah 5 in the IRVH

Nehemiah 5 in the IRVK

Nehemiah 5 in the IRVM

Nehemiah 5 in the IRVM2

Nehemiah 5 in the IRVO

Nehemiah 5 in the IRVP

Nehemiah 5 in the IRVT

Nehemiah 5 in the IRVT2

Nehemiah 5 in the IRVU

Nehemiah 5 in the ISVN

Nehemiah 5 in the JSNT

Nehemiah 5 in the KAPI

Nehemiah 5 in the KBT1ETNIK

Nehemiah 5 in the KBV

Nehemiah 5 in the KJV

Nehemiah 5 in the KNFD

Nehemiah 5 in the LBA

Nehemiah 5 in the LBLA

Nehemiah 5 in the LNT

Nehemiah 5 in the LSV

Nehemiah 5 in the MAAL

Nehemiah 5 in the MBV

Nehemiah 5 in the MBV2

Nehemiah 5 in the MHNT

Nehemiah 5 in the MKNFD

Nehemiah 5 in the MNG

Nehemiah 5 in the MNT

Nehemiah 5 in the MNT2

Nehemiah 5 in the MRS1T

Nehemiah 5 in the NAA

Nehemiah 5 in the NASB

Nehemiah 5 in the NBLA

Nehemiah 5 in the NBS

Nehemiah 5 in the NBVTP

Nehemiah 5 in the NET2

Nehemiah 5 in the NIV11

Nehemiah 5 in the NNT

Nehemiah 5 in the NNT2

Nehemiah 5 in the NNT3

Nehemiah 5 in the PDDPT

Nehemiah 5 in the PFNT

Nehemiah 5 in the RMNT

Nehemiah 5 in the SBIAS

Nehemiah 5 in the SBIBS

Nehemiah 5 in the SBIBS2

Nehemiah 5 in the SBICS

Nehemiah 5 in the SBIDS

Nehemiah 5 in the SBIGS

Nehemiah 5 in the SBIHS

Nehemiah 5 in the SBIIS

Nehemiah 5 in the SBIIS2

Nehemiah 5 in the SBIIS3

Nehemiah 5 in the SBIKS

Nehemiah 5 in the SBIKS2

Nehemiah 5 in the SBIMS

Nehemiah 5 in the SBIOS

Nehemiah 5 in the SBIPS

Nehemiah 5 in the SBISS

Nehemiah 5 in the SBITS

Nehemiah 5 in the SBITS2

Nehemiah 5 in the SBITS3

Nehemiah 5 in the SBITS4

Nehemiah 5 in the SBIUS

Nehemiah 5 in the SBIVS

Nehemiah 5 in the SBT

Nehemiah 5 in the SBT1E

Nehemiah 5 in the SCHL

Nehemiah 5 in the SNT

Nehemiah 5 in the SUSU

Nehemiah 5 in the SUSU2

Nehemiah 5 in the SYNO

Nehemiah 5 in the TBIAOTANT

Nehemiah 5 in the TBT1E

Nehemiah 5 in the TBT1E2

Nehemiah 5 in the TFTIP

Nehemiah 5 in the TFTU

Nehemiah 5 in the TGNTATF3T

Nehemiah 5 in the THAI

Nehemiah 5 in the TNFD

Nehemiah 5 in the TNT

Nehemiah 5 in the TNTIK

Nehemiah 5 in the TNTIL

Nehemiah 5 in the TNTIN

Nehemiah 5 in the TNTIP

Nehemiah 5 in the TNTIZ

Nehemiah 5 in the TOMA

Nehemiah 5 in the TTENT

Nehemiah 5 in the UBG

Nehemiah 5 in the UGV

Nehemiah 5 in the UGV2

Nehemiah 5 in the UGV3

Nehemiah 5 in the VBL

Nehemiah 5 in the VDCC

Nehemiah 5 in the YALU

Nehemiah 5 in the YAPE

Nehemiah 5 in the YBVTP

Nehemiah 5 in the ZBP