Isaiah 49 (BOYCB)

1 Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin erékùṣù:gbọ́ èyí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè jíjìnnà réré:kí a tó bí mi OLÚWA ti pè mí;láti ìgbà bíbí mi ni ó ti dá orúkọ mi. 2 Ó ṣe ẹnu mi bí idà tí a pọ́n,ní abẹ́ òjìji ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti pa mí mọ́:ó ṣe mí ní ọfà tí a ti dán,ó sì fi mí pamọ́ sínú àpò rẹ̀. 3 Ó sọ fún mi pé, “Ìránṣẹ́ mi ni ìwọ í ṣe,Israẹli nínú ẹni tí n ó ti fi ògo mi hàn.” 4 Ṣùgbọ́n èmi sọ pé, “Mo ti ṣe wàhálà lórí asán;mo ti lo gbogbo ipá mi lórí asán àti ìmúlẹ̀mófo.Síbẹ̀síbẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi ṣì wà lọ́wọ́ OLÚWA,èrè mi sì ń bẹ pẹ̀lú Ọlọ́run mi.” 5 Nísinsin yìí OLÚWA wí péẹni tí ó mọ̀ mí láti inú wá láti jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀láti mú Jakọbu padà tọ̀ mí wáàti láti kó Israẹli jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,nítorí pé a bọ̀wọ̀ fún mi ní ojú OLÚWAỌlọ́run mi sì ti jẹ́ agbára mi, 6 Òun wí pé:“Ó jẹ́ ohun kékeré fún ọ láti jẹ́ ìránṣẹ́ miláti mú ẹ̀yà Jakọbu padà bọ̀ sípòàti láti mú àwọn ti Israẹli tí mo ti pamọ́.Èmi yóò sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn kèfèrí,kí ìwọ kí ó lè mú ìgbàlà mi wásí òpin ilẹ̀ ayé.” 7 Ohun tí OLÚWA wí nìyìí,Olùdáǹdè àti Ẹni Mímọ́ Israẹli—sí ẹni náà tí a gàn tí a sì kórìíralọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè,sí ìránṣẹ́ àwọn aláṣẹ:“Àwọn ọba yóò rí ọ wọn yóò sì dìde sókè,àwọn ọmọ ọba yóò rí i wọn yóò sì wólẹ̀,nítorí OLÚWA ẹni tí í ṣe olóòtítọ́,Ẹni Mímọ́ Israẹli tí ó ti yàn ọ́.” 8 Ohun tí OLÚWA wí nìyìí:“Ní àkókò ojúrere mi, èmi yóò dá ọ lóhùn,àti ní ọjọ́ ìgbàlà, èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́;Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn,láti mú ilẹ̀ padà bọ̀ sípòàti láti ṣe àtúnpín ogún rẹ̀ tí ó ti dahoro, 9 láti sọ fún àwọn ìgbèkùn pé, ‘Ẹ jáde wá,’àti fún àwọn tí ó wà nínú òkùnkùn pé, ‘Ẹ gba òmìnira!’ “Wọn yóò máa jẹ ní ẹ̀bá ọ̀nààti koríko tútù lórí òkè aláìléwéko. 10 Ebi kì yóò pa wọ́n bẹ́ẹ̀ ni òǹgbẹ kì yóò gbẹ wọ́n,tàbí kí ooru inú aṣálẹ̀ tàbí oòrùn kí ó pa wọ́n.Ẹni tí ó ṣàánú fún wọn ni yóò máa tọ́ wọn,tí yóò sì mú wọn lọ sí ibi orísun omi. 11 Èmi yóò sọ gbogbo àwọn òkè ńlá mi di ojú ọ̀nààti gbogbo òpópónà mi ni a ó gbé sókè. 12 Kíyèsi i, wọn yóò wá láti ọ̀nà jíjìnàwọn díẹ̀ láti àríwá àti àwọn díẹ̀ láti ìwọ̀-oòrùn,àwọn díẹ̀ láti ẹkùn Siene.” 13 Ẹ hó fún ayọ̀, ẹyin ọ̀run;yọ̀, ìwọ ilẹ̀ ayé;bú sórin, ẹ̀yin òkè ńlá!Nítorí OLÚWA tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínúyóò sì ṣàánú fún àwọn ẹnití a ń pọ́n lójú. 14 Ṣùgbọ́n Sioni sọ pé, “OLÚWA ti kọ̀ mí sílẹ̀,Olúwa ti gbàgbé è mi.” 15 “Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ọmú rẹ̀kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí?Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbé,Èmi kì yóò gbàgbé rẹ! 16 Kíyèsi i, mo ti kọ ọ́ sí àtẹ́lẹwọ́ miògiri rẹ wà níwájú mi nígbà gbogbo. 17 Àwọn ọmọ rẹ ti kánjú padà,àti àwọn tí ó sọ ọ́ dahoro ti padà lẹ́yìn rẹ. 18 Gbójú rẹ sókè kí o sì wò yíká;gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ kórajọwọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ.Níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè,” ni OLÚWA wí,“Ìwọ yóò wọ gbogbo wọ́n gẹ́gẹ́ bí ohun ọ̀ṣọ́;ìwọ yóò wọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ìyàwó. 19 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí run ọ́, a sì sọ ọ́ di ahorotí gbogbo ilẹ̀ rẹ sì di ìparun,ní ìsinsin yìí, ìwọ yóò kéré jù fún àwọn ènìyàn rẹ,bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó jẹ ọ́ run ni yóòwà láti ọ̀nà jíjìn réré. 20 Àwọn ọmọ tí a bí ní àkókò ọ̀fọ̀ rẹyóò sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ,‘Ibi yìí ti kéré jù fún wa;ẹ fún wa láyè sí i tí a ó máa gbé.’ 21 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní ọkàn rẹ pé,‘Ta ló bí àwọn yìí fún mi?Mo ti ṣọ̀fọ̀ mo sì yàgàn;a sọ mi di àtìpó a sì kọ̀ mí sílẹ̀.Ta ló wo àwọn yìí dàgbà?A fi èmi nìkan sílẹ̀,ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí níbo ni wọ́n ti wá?’ ” 22 Ohun tí OLÚWA Olódùmarè wí nìyìí,“Kíyèsi i, Èmi yóò ké sí àwọn aláìkọlà,Èmi yóò gbé àsíá mi sókè sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn;wọn yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín wá ní apá wọnwọn yóò sì gbé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrinní èjìká wọn. 23 Àwọn ọba ni yóò jẹ́ alágbàtọ́ baba fún ọ,àwọn ayaba wọn ni yóò sì jẹ́ ìyá-alágbàtọ́.Wọn yóò foríbalẹ̀ ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀;wọn yóò máa lá erùpẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ.Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni OLÚWA;gbogbo àwọn tí wọ́n ní ìrètí nínú mini a kì yóò jákulẹ̀.” 24 Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun,tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú? 25 Ṣùgbọ́n ohun tí OLÚWA wí nìyìí:“Bẹ́ẹ̀ ni, a ó gba àwọn ìgbèkùn lọ́wọ́ àwọn jagunjagun,àti ìkógun lọ́wọ́ àwọn akíkanjú;ẹni tí ó bá ọ jà ni èmi ó bá jà,àti àwọn ọmọ rẹ ni èmi ó gbàlà. 26 Èmi yóò mú kí àwọn aninilára rẹ̀ jẹ ẹran-ara wọn;wọn yóò mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn yó bí ẹni mu wáìnì.Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn yóò mọ̀pé, Èmi, OLÚWA, èmi ni Olùgbàlà rẹ,Olùdáǹdè rẹ, Alágbára kan ṣoṣo ti Jakọbu.”

In Other Versions

Isaiah 49 in the ANGEFD

Isaiah 49 in the ANTPNG2D

Isaiah 49 in the AS21

Isaiah 49 in the BAGH

Isaiah 49 in the BBPNG

Isaiah 49 in the BBT1E

Isaiah 49 in the BDS

Isaiah 49 in the BEV

Isaiah 49 in the BHAD

Isaiah 49 in the BIB

Isaiah 49 in the BLPT

Isaiah 49 in the BNT

Isaiah 49 in the BNTABOOT

Isaiah 49 in the BNTLV

Isaiah 49 in the BOATCB

Isaiah 49 in the BOATCB2

Isaiah 49 in the BOBCV

Isaiah 49 in the BOCNT

Isaiah 49 in the BOECS

Isaiah 49 in the BOGWICC

Isaiah 49 in the BOHCB

Isaiah 49 in the BOHCV

Isaiah 49 in the BOHLNT

Isaiah 49 in the BOHNTLTAL

Isaiah 49 in the BOICB

Isaiah 49 in the BOILNTAP

Isaiah 49 in the BOITCV

Isaiah 49 in the BOKCV

Isaiah 49 in the BOKCV2

Isaiah 49 in the BOKHWOG

Isaiah 49 in the BOKSSV

Isaiah 49 in the BOLCB

Isaiah 49 in the BOLCB2

Isaiah 49 in the BOMCV

Isaiah 49 in the BONAV

Isaiah 49 in the BONCB

Isaiah 49 in the BONLT

Isaiah 49 in the BONUT2

Isaiah 49 in the BOPLNT

Isaiah 49 in the BOSCB

Isaiah 49 in the BOSNC

Isaiah 49 in the BOTLNT

Isaiah 49 in the BOVCB

Isaiah 49 in the BPBB

Isaiah 49 in the BPH

Isaiah 49 in the BSB

Isaiah 49 in the CCB

Isaiah 49 in the CUV

Isaiah 49 in the CUVS

Isaiah 49 in the DBT

Isaiah 49 in the DGDNT

Isaiah 49 in the DHNT

Isaiah 49 in the DNT

Isaiah 49 in the ELBE

Isaiah 49 in the EMTV

Isaiah 49 in the ESV

Isaiah 49 in the FBV

Isaiah 49 in the FEB

Isaiah 49 in the GGMNT

Isaiah 49 in the GNT

Isaiah 49 in the HARY

Isaiah 49 in the HNT

Isaiah 49 in the IRVA

Isaiah 49 in the IRVB

Isaiah 49 in the IRVG

Isaiah 49 in the IRVH

Isaiah 49 in the IRVK

Isaiah 49 in the IRVM

Isaiah 49 in the IRVM2

Isaiah 49 in the IRVO

Isaiah 49 in the IRVP

Isaiah 49 in the IRVT

Isaiah 49 in the IRVT2

Isaiah 49 in the IRVU

Isaiah 49 in the ISVN

Isaiah 49 in the JSNT

Isaiah 49 in the KAPI

Isaiah 49 in the KBT1ETNIK

Isaiah 49 in the KBV

Isaiah 49 in the KJV

Isaiah 49 in the KNFD

Isaiah 49 in the LBA

Isaiah 49 in the LBLA

Isaiah 49 in the LNT

Isaiah 49 in the LSV

Isaiah 49 in the MAAL

Isaiah 49 in the MBV

Isaiah 49 in the MBV2

Isaiah 49 in the MHNT

Isaiah 49 in the MKNFD

Isaiah 49 in the MNG

Isaiah 49 in the MNT

Isaiah 49 in the MNT2

Isaiah 49 in the MRS1T

Isaiah 49 in the NAA

Isaiah 49 in the NASB

Isaiah 49 in the NBLA

Isaiah 49 in the NBS

Isaiah 49 in the NBVTP

Isaiah 49 in the NET2

Isaiah 49 in the NIV11

Isaiah 49 in the NNT

Isaiah 49 in the NNT2

Isaiah 49 in the NNT3

Isaiah 49 in the PDDPT

Isaiah 49 in the PFNT

Isaiah 49 in the RMNT

Isaiah 49 in the SBIAS

Isaiah 49 in the SBIBS

Isaiah 49 in the SBIBS2

Isaiah 49 in the SBICS

Isaiah 49 in the SBIDS

Isaiah 49 in the SBIGS

Isaiah 49 in the SBIHS

Isaiah 49 in the SBIIS

Isaiah 49 in the SBIIS2

Isaiah 49 in the SBIIS3

Isaiah 49 in the SBIKS

Isaiah 49 in the SBIKS2

Isaiah 49 in the SBIMS

Isaiah 49 in the SBIOS

Isaiah 49 in the SBIPS

Isaiah 49 in the SBISS

Isaiah 49 in the SBITS

Isaiah 49 in the SBITS2

Isaiah 49 in the SBITS3

Isaiah 49 in the SBITS4

Isaiah 49 in the SBIUS

Isaiah 49 in the SBIVS

Isaiah 49 in the SBT

Isaiah 49 in the SBT1E

Isaiah 49 in the SCHL

Isaiah 49 in the SNT

Isaiah 49 in the SUSU

Isaiah 49 in the SUSU2

Isaiah 49 in the SYNO

Isaiah 49 in the TBIAOTANT

Isaiah 49 in the TBT1E

Isaiah 49 in the TBT1E2

Isaiah 49 in the TFTIP

Isaiah 49 in the TFTU

Isaiah 49 in the TGNTATF3T

Isaiah 49 in the THAI

Isaiah 49 in the TNFD

Isaiah 49 in the TNT

Isaiah 49 in the TNTIK

Isaiah 49 in the TNTIL

Isaiah 49 in the TNTIN

Isaiah 49 in the TNTIP

Isaiah 49 in the TNTIZ

Isaiah 49 in the TOMA

Isaiah 49 in the TTENT

Isaiah 49 in the UBG

Isaiah 49 in the UGV

Isaiah 49 in the UGV2

Isaiah 49 in the UGV3

Isaiah 49 in the VBL

Isaiah 49 in the VDCC

Isaiah 49 in the YALU

Isaiah 49 in the YAPE

Isaiah 49 in the YBVTP

Isaiah 49 in the ZBP