Nehemiah 8 (BOYCB)

1 gbogbo àwọn ènìyàn kó ara wọn jọ bí ẹnìkan ní gbangba ìta níwájú ibodè omi. Wọ́n sọ fún Esra akọ̀wé pé kí ó gbé ìwé òfin Mose jáde, èyí tí OLÚWA ti pàṣẹ fún Israẹli. 2 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje ni àlùfáà Esra gbé ìwé òfin jáde ní iwájú ìjọ ènìyàn, èyí tí ó jẹ́ àpapọ̀ ọkùnrin àti obìnrin àti gbogbo àwọn ènìyàn tí wọ́n le è gbọ́ ọ ní àgbọ́yé. 3 Ó kà á sókè láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán bí ó ti kọjú sí ìta ní iwájú ibodè omi ní ojú u gbogbo ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ènìyàn tókù tí òye le è yé tí wọ́n wà níbẹ̀. Gbogbo ènìyàn sì fetísílẹ̀ sí ìwé òfin náà pẹ̀lú ìfarabalẹ̀. 4 Akọ̀wé Esra dìde dúró lórí i pẹpẹ ìdúrólé tí a fi igi kàn fún ètò yìí. Ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ọ̀tún ni Mattitiah, Ṣema, Anaiah, Uriah, Hilkiah àti Maaseiah gbé dúró sí, ní ẹ̀gbẹ́ òsì rẹ̀ ní Pedaiah, Misaeli, Malkiah, Haṣumu, Haṣabadana, Sekariah àti Meṣullamu dúró sí. 5 Esra ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn sì le rí í nítorí ó dúró níbi tí ó ga ju gbogbo ènìyàn lọ; bí ó sì ti ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn dìde dúró. 6 Esra yin OLÚWA, Ọlọ́run alágbára; gbogbo ènìyàn gbé ọwọ́ wọn sókè, wọ́n sì wí pé, “Àmín! Àmín!” Nígbà náà ni wọ́n wólẹ̀ wọ́n sì sin OLÚWA ní ìdojúbolẹ̀. 7 Àwọn Lefi—Jeṣua, Bani, Ṣerebiah, Jamini, Akkubu, Ṣabbetai, Hodiah, Maaseiah, Kelita, Asariah, Josabadi, Hanani àti Pelaiah—kọ́ wọn ni òfin náà bí àwọn ènìyàn ṣe wà ní ìdúró síbẹ̀. 8 Wọ́n kà láti inú ìwé òfin Ọlọ́run, wọ́n túmọ̀ rẹ̀, wọ́n ṣe àlàyé kí ohun tí wọ́n kà bá à le yé àwọn ènìyàn yékéyéké. 9 Nígbà náà ni Nehemiah tí ó jẹ́ baálẹ̀, Esra àlùfáà àti akọ̀wé, àti àwọn Lefi tí wọ́n ń kọ́ àwọn ènìyàn wí fún gbogbo wọn pé, “Ọjọ́ yìí jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún OLÚWA Ọlọ́run yín. Ẹ má ṣe ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún,” nítorí gbogbo àwọn ènìyàn ti ń sọkún bí wọ́n ti ń tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ inú òfin náà. 10 Nehemiah wí pé, “Ẹ lọ kí ẹ gbádùn oúnjẹ tí ẹ yàn láàyò kí ẹ sì mú ohun dídùn, kí ẹ sì mú díẹ̀ ránṣẹ́ sí àwọn tí kò ní. Ọjọ́ yìí, mímọ́ ni fún Olúwa wa. Ẹ má ṣe banújẹ́, nítorí ayọ̀ OLÚWA ni agbára yín.” 11 Àwọn ọmọ Lefi mú kí gbogbo ènìyàn dákẹ́ jẹ́, wọ́n wí pé, “Ẹ dákẹ́, nítorí mímọ́ ni ọjọ́ yìí. Ẹ má ṣe banújẹ́.” 12 Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn lọ láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì fi ìpín oúnjẹ ránṣẹ́, wọ́n sì ṣe àjọyọ̀ pẹ̀lú ayọ̀ ńlá, nítorí báyìí àwọn òfin tí a sọ di mímọ́ fun wọn ti yé wọn. 13 Ní ọjọ́ kejì oṣù náà, àwọn olórí, gbogbo ìdílé, àti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, péjọ sọ́dọ̀ Esra akọ̀wé, wọ́n fi ara balẹ̀ láti fetí sí àwọn ọ̀rọ̀ òfin. 14 Wọ́n ri ní àkọsílẹ̀ nínú ìwé òfin, èyí tí OLÚWA ti pa ní àṣẹ nípasẹ̀ Mose, kí àwọn ọmọ Israẹli gbé inú àgọ́ ní àkókò àjọ àgọ́ oṣù keje 15 àti kí wọn kéde ọ̀rọ̀ yìí, kí wọn sì tàn án kálẹ̀ ní gbogbo ìlú wọn àti ní Jerusalẹmu: “Ẹ jáde lọ sí ìlú olókè, kí ẹ mú àwọn ẹ̀ka inú olifi àti ẹ̀ka igi olifi igbó, àti láti inú maritili, àwọn imọ̀ ọ̀pẹ àti àwọn igi tí ó léwé dáradára wá, láti ṣe àgọ́”—gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́. 16 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn jáde lọ, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀ka wá, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn sí orí òrùlé ara wọn, ní àgbàlá wọn àti ní àgbàlá ilé Ọlọ́run àti ní ìta gbangba lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè omi àti èyí tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè Efraimu. 17 Gbogbo ìjọ ènìyàn tí wọ́n padà láti ìgbèkùn kọ́ àgọ́, wọ́n sì ń gbé inú wọn. Láti ọjọ́ Jeṣua ọmọ Nuni títí di ọjọ́ náà, àwọn ọmọ Israẹli kò tí ì ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀ bí irú èyí. Ayọ̀ ọ wọn sì pọ̀. 18 Esra kà nínú ìwé òfin Ọlọ́run, bí ọjọ́ ṣe ń gorí ọjọ́, láti ọjọ́ kìn-ín-ní dé ọjọ́ ìkẹyìn. Wọ́n ṣe àjọyọ̀ àjọ náà fún ọjọ́ méje, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n ní àpéjọ, ní ìbámu pẹ̀lú òfin.

In Other Versions

Nehemiah 8 in the ANGEFD

Nehemiah 8 in the ANTPNG2D

Nehemiah 8 in the AS21

Nehemiah 8 in the BAGH

Nehemiah 8 in the BBPNG

Nehemiah 8 in the BBT1E

Nehemiah 8 in the BDS

Nehemiah 8 in the BEV

Nehemiah 8 in the BHAD

Nehemiah 8 in the BIB

Nehemiah 8 in the BLPT

Nehemiah 8 in the BNT

Nehemiah 8 in the BNTABOOT

Nehemiah 8 in the BNTLV

Nehemiah 8 in the BOATCB

Nehemiah 8 in the BOATCB2

Nehemiah 8 in the BOBCV

Nehemiah 8 in the BOCNT

Nehemiah 8 in the BOECS

Nehemiah 8 in the BOGWICC

Nehemiah 8 in the BOHCB

Nehemiah 8 in the BOHCV

Nehemiah 8 in the BOHLNT

Nehemiah 8 in the BOHNTLTAL

Nehemiah 8 in the BOICB

Nehemiah 8 in the BOILNTAP

Nehemiah 8 in the BOITCV

Nehemiah 8 in the BOKCV

Nehemiah 8 in the BOKCV2

Nehemiah 8 in the BOKHWOG

Nehemiah 8 in the BOKSSV

Nehemiah 8 in the BOLCB

Nehemiah 8 in the BOLCB2

Nehemiah 8 in the BOMCV

Nehemiah 8 in the BONAV

Nehemiah 8 in the BONCB

Nehemiah 8 in the BONLT

Nehemiah 8 in the BONUT2

Nehemiah 8 in the BOPLNT

Nehemiah 8 in the BOSCB

Nehemiah 8 in the BOSNC

Nehemiah 8 in the BOTLNT

Nehemiah 8 in the BOVCB

Nehemiah 8 in the BPBB

Nehemiah 8 in the BPH

Nehemiah 8 in the BSB

Nehemiah 8 in the CCB

Nehemiah 8 in the CUV

Nehemiah 8 in the CUVS

Nehemiah 8 in the DBT

Nehemiah 8 in the DGDNT

Nehemiah 8 in the DHNT

Nehemiah 8 in the DNT

Nehemiah 8 in the ELBE

Nehemiah 8 in the EMTV

Nehemiah 8 in the ESV

Nehemiah 8 in the FBV

Nehemiah 8 in the FEB

Nehemiah 8 in the GGMNT

Nehemiah 8 in the GNT

Nehemiah 8 in the HARY

Nehemiah 8 in the HNT

Nehemiah 8 in the IRVA

Nehemiah 8 in the IRVB

Nehemiah 8 in the IRVG

Nehemiah 8 in the IRVH

Nehemiah 8 in the IRVK

Nehemiah 8 in the IRVM

Nehemiah 8 in the IRVM2

Nehemiah 8 in the IRVO

Nehemiah 8 in the IRVP

Nehemiah 8 in the IRVT

Nehemiah 8 in the IRVT2

Nehemiah 8 in the IRVU

Nehemiah 8 in the ISVN

Nehemiah 8 in the JSNT

Nehemiah 8 in the KAPI

Nehemiah 8 in the KBT1ETNIK

Nehemiah 8 in the KBV

Nehemiah 8 in the KJV

Nehemiah 8 in the KNFD

Nehemiah 8 in the LBA

Nehemiah 8 in the LBLA

Nehemiah 8 in the LNT

Nehemiah 8 in the LSV

Nehemiah 8 in the MAAL

Nehemiah 8 in the MBV

Nehemiah 8 in the MBV2

Nehemiah 8 in the MHNT

Nehemiah 8 in the MKNFD

Nehemiah 8 in the MNG

Nehemiah 8 in the MNT

Nehemiah 8 in the MNT2

Nehemiah 8 in the MRS1T

Nehemiah 8 in the NAA

Nehemiah 8 in the NASB

Nehemiah 8 in the NBLA

Nehemiah 8 in the NBS

Nehemiah 8 in the NBVTP

Nehemiah 8 in the NET2

Nehemiah 8 in the NIV11

Nehemiah 8 in the NNT

Nehemiah 8 in the NNT2

Nehemiah 8 in the NNT3

Nehemiah 8 in the PDDPT

Nehemiah 8 in the PFNT

Nehemiah 8 in the RMNT

Nehemiah 8 in the SBIAS

Nehemiah 8 in the SBIBS

Nehemiah 8 in the SBIBS2

Nehemiah 8 in the SBICS

Nehemiah 8 in the SBIDS

Nehemiah 8 in the SBIGS

Nehemiah 8 in the SBIHS

Nehemiah 8 in the SBIIS

Nehemiah 8 in the SBIIS2

Nehemiah 8 in the SBIIS3

Nehemiah 8 in the SBIKS

Nehemiah 8 in the SBIKS2

Nehemiah 8 in the SBIMS

Nehemiah 8 in the SBIOS

Nehemiah 8 in the SBIPS

Nehemiah 8 in the SBISS

Nehemiah 8 in the SBITS

Nehemiah 8 in the SBITS2

Nehemiah 8 in the SBITS3

Nehemiah 8 in the SBITS4

Nehemiah 8 in the SBIUS

Nehemiah 8 in the SBIVS

Nehemiah 8 in the SBT

Nehemiah 8 in the SBT1E

Nehemiah 8 in the SCHL

Nehemiah 8 in the SNT

Nehemiah 8 in the SUSU

Nehemiah 8 in the SUSU2

Nehemiah 8 in the SYNO

Nehemiah 8 in the TBIAOTANT

Nehemiah 8 in the TBT1E

Nehemiah 8 in the TBT1E2

Nehemiah 8 in the TFTIP

Nehemiah 8 in the TFTU

Nehemiah 8 in the TGNTATF3T

Nehemiah 8 in the THAI

Nehemiah 8 in the TNFD

Nehemiah 8 in the TNT

Nehemiah 8 in the TNTIK

Nehemiah 8 in the TNTIL

Nehemiah 8 in the TNTIN

Nehemiah 8 in the TNTIP

Nehemiah 8 in the TNTIZ

Nehemiah 8 in the TOMA

Nehemiah 8 in the TTENT

Nehemiah 8 in the UBG

Nehemiah 8 in the UGV

Nehemiah 8 in the UGV2

Nehemiah 8 in the UGV3

Nehemiah 8 in the VBL

Nehemiah 8 in the VDCC

Nehemiah 8 in the YALU

Nehemiah 8 in the YAPE

Nehemiah 8 in the YBVTP

Nehemiah 8 in the ZBP