Jeremiah 50 (BOYCB)

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí OLÚWA fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli: 2 “Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde,kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé,‘A kó Babeli,ojú tí Beli,a fọ́ Merodaki túútúú,ojú ti àwọn ère rẹ̀,a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’ 3 Àwọn ìlú ní apá àríwá yóòsì máa gbóguntì wọ́n.Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóòsá kúrò ní ìlú yìí. 4 “Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,”ni OLÚWA wí,“Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá,àwọn, àti àwọn ọmọ Juda,wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí OLÚWA Ọlọ́run wọn. 5 Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni,ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀,wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ OLÚWAní májẹ̀mú ayérayé,tí a kì yóò gbàgbé. 6 “Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù,àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà,wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkèwọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré,wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn. 7 Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹàwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀binítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí OLÚWA ibùgbéòdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’ 8 “Jáde kúrò ní Babeli,ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀,kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran. 9 Nítorí pé èmi yóò ru,bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdèńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀;láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóòdàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo. 10 A ó dààmú Babeli,gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,”ni OLÚWA wí. 11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀,ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìnfi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù,ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin. 12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọyóò sì gba ìtìjú.Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè,ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá. 13 Nítorí ìbínú OLÚWA, kì yóò ní olùgbé;ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀.Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóòfi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀. 14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeliàti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà.Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí OLÚWA. 15 Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà!Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀,níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san OLÚWA,gbẹ̀san lára rẹ̀.Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn. 16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli,àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè!Nítorí idà àwọn aninilárajẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀,kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀. 17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri,kìnnìún sì ti lé e lọ.Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ,àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babelifa egungun rẹ̀ ya.” 18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí OLÚWA Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí,“Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria. 19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹlipadà wá pápá oko tútù rẹ̀òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani,a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkèEfraimu àti ní Gileadi. 20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,”ni OLÚWA wí,“À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli,ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun;àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankannítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí. 21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọntí ó ń gbé ní Pekodi.Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,”ni OLÚWA wí,“Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ. 22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náàìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá. 23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó,lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé!Báwo ní Babeli ti di ahoroni àárín àwọn orílẹ̀-èdè. 24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀fún ọ ìwọ Babeli,kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀,o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako OLÚWA. 25 OLÚWA ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde,nítorí pé OLÚWA Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogunti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli. 26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo,sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀,ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà,kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun,ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un. 27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ,jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n!Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé,àkókò ìbẹ̀wò wọn. 28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá,sì sọ ní Sioni,bí OLÚWA Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san,ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀. 29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli,ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà.Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe,ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéragasí OLÚWA, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli. 30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọnológun lẹ́nu mọ́,”ní OLÚWA wí. 31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,”ni Olúwa, OLÚWA àwọn ọmọ-ogun wí,“nítorí ọjọ́ rẹ ti dé,àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò. 32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú,kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde.Èmi yóò tan iná ní ìlú náà,èyí tí yóò sì jo run.” 33 Èyí ni ohun tí OLÚWA àwọn ọmọ-ogun sọ:“A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹlilójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú.Gbogbo àwọn tí ó kó wọnnígbèkùn dì wọn mú ṣinṣinwọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà. 34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, OLÚWA Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀.Yóò sì gbe ìjà wọn jà,kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà;ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli. 35 “Idà lórí àwọn Babeli!”ni OLÚWA wí,“lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli,àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin. 36 Idà lórí àwọn wòlíì èkéwọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun,wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù. 37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀.Wọn yóò di obìnrin.Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀! 38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ.Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère,àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù. 39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijùpẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀,abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀,a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé,bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran. 40 Gẹ́gẹ́ bí OLÚWA ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorrapẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,”ni OLÚWA wí,“torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀;ènìyàn ki yóò gbé nínú rè. 41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá;orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ńgbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé. 42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun,wọ́n burú wọn kò sì ní àánú.Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ.Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli. 43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn,ọwọ́ wọn sì rọ,ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí. 44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordanisí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá,Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá.Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀?Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí?Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?” 45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí OLÚWA sọ nípa Babeli,ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli:n ó sì pa agbo ẹran wọn run. 46 Ní ohùn igbe ńlá pé;a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì,a sì gbọ́ igbe náàláàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

In Other Versions

Jeremiah 50 in the ANGEFD

Jeremiah 50 in the ANTPNG2D

Jeremiah 50 in the AS21

Jeremiah 50 in the BAGH

Jeremiah 50 in the BBPNG

Jeremiah 50 in the BBT1E

Jeremiah 50 in the BDS

Jeremiah 50 in the BEV

Jeremiah 50 in the BHAD

Jeremiah 50 in the BIB

Jeremiah 50 in the BLPT

Jeremiah 50 in the BNT

Jeremiah 50 in the BNTABOOT

Jeremiah 50 in the BNTLV

Jeremiah 50 in the BOATCB

Jeremiah 50 in the BOATCB2

Jeremiah 50 in the BOBCV

Jeremiah 50 in the BOCNT

Jeremiah 50 in the BOECS

Jeremiah 50 in the BOGWICC

Jeremiah 50 in the BOHCB

Jeremiah 50 in the BOHCV

Jeremiah 50 in the BOHLNT

Jeremiah 50 in the BOHNTLTAL

Jeremiah 50 in the BOICB

Jeremiah 50 in the BOILNTAP

Jeremiah 50 in the BOITCV

Jeremiah 50 in the BOKCV

Jeremiah 50 in the BOKCV2

Jeremiah 50 in the BOKHWOG

Jeremiah 50 in the BOKSSV

Jeremiah 50 in the BOLCB

Jeremiah 50 in the BOLCB2

Jeremiah 50 in the BOMCV

Jeremiah 50 in the BONAV

Jeremiah 50 in the BONCB

Jeremiah 50 in the BONLT

Jeremiah 50 in the BONUT2

Jeremiah 50 in the BOPLNT

Jeremiah 50 in the BOSCB

Jeremiah 50 in the BOSNC

Jeremiah 50 in the BOTLNT

Jeremiah 50 in the BOVCB

Jeremiah 50 in the BPBB

Jeremiah 50 in the BPH

Jeremiah 50 in the BSB

Jeremiah 50 in the CCB

Jeremiah 50 in the CUV

Jeremiah 50 in the CUVS

Jeremiah 50 in the DBT

Jeremiah 50 in the DGDNT

Jeremiah 50 in the DHNT

Jeremiah 50 in the DNT

Jeremiah 50 in the ELBE

Jeremiah 50 in the EMTV

Jeremiah 50 in the ESV

Jeremiah 50 in the FBV

Jeremiah 50 in the FEB

Jeremiah 50 in the GGMNT

Jeremiah 50 in the GNT

Jeremiah 50 in the HARY

Jeremiah 50 in the HNT

Jeremiah 50 in the IRVA

Jeremiah 50 in the IRVB

Jeremiah 50 in the IRVG

Jeremiah 50 in the IRVH

Jeremiah 50 in the IRVK

Jeremiah 50 in the IRVM

Jeremiah 50 in the IRVM2

Jeremiah 50 in the IRVO

Jeremiah 50 in the IRVP

Jeremiah 50 in the IRVT

Jeremiah 50 in the IRVT2

Jeremiah 50 in the IRVU

Jeremiah 50 in the ISVN

Jeremiah 50 in the JSNT

Jeremiah 50 in the KAPI

Jeremiah 50 in the KBT1ETNIK

Jeremiah 50 in the KBV

Jeremiah 50 in the KJV

Jeremiah 50 in the KNFD

Jeremiah 50 in the LBA

Jeremiah 50 in the LBLA

Jeremiah 50 in the LNT

Jeremiah 50 in the LSV

Jeremiah 50 in the MAAL

Jeremiah 50 in the MBV

Jeremiah 50 in the MBV2

Jeremiah 50 in the MHNT

Jeremiah 50 in the MKNFD

Jeremiah 50 in the MNG

Jeremiah 50 in the MNT

Jeremiah 50 in the MNT2

Jeremiah 50 in the MRS1T

Jeremiah 50 in the NAA

Jeremiah 50 in the NASB

Jeremiah 50 in the NBLA

Jeremiah 50 in the NBS

Jeremiah 50 in the NBVTP

Jeremiah 50 in the NET2

Jeremiah 50 in the NIV11

Jeremiah 50 in the NNT

Jeremiah 50 in the NNT2

Jeremiah 50 in the NNT3

Jeremiah 50 in the PDDPT

Jeremiah 50 in the PFNT

Jeremiah 50 in the RMNT

Jeremiah 50 in the SBIAS

Jeremiah 50 in the SBIBS

Jeremiah 50 in the SBIBS2

Jeremiah 50 in the SBICS

Jeremiah 50 in the SBIDS

Jeremiah 50 in the SBIGS

Jeremiah 50 in the SBIHS

Jeremiah 50 in the SBIIS

Jeremiah 50 in the SBIIS2

Jeremiah 50 in the SBIIS3

Jeremiah 50 in the SBIKS

Jeremiah 50 in the SBIKS2

Jeremiah 50 in the SBIMS

Jeremiah 50 in the SBIOS

Jeremiah 50 in the SBIPS

Jeremiah 50 in the SBISS

Jeremiah 50 in the SBITS

Jeremiah 50 in the SBITS2

Jeremiah 50 in the SBITS3

Jeremiah 50 in the SBITS4

Jeremiah 50 in the SBIUS

Jeremiah 50 in the SBIVS

Jeremiah 50 in the SBT

Jeremiah 50 in the SBT1E

Jeremiah 50 in the SCHL

Jeremiah 50 in the SNT

Jeremiah 50 in the SUSU

Jeremiah 50 in the SUSU2

Jeremiah 50 in the SYNO

Jeremiah 50 in the TBIAOTANT

Jeremiah 50 in the TBT1E

Jeremiah 50 in the TBT1E2

Jeremiah 50 in the TFTIP

Jeremiah 50 in the TFTU

Jeremiah 50 in the TGNTATF3T

Jeremiah 50 in the THAI

Jeremiah 50 in the TNFD

Jeremiah 50 in the TNT

Jeremiah 50 in the TNTIK

Jeremiah 50 in the TNTIL

Jeremiah 50 in the TNTIN

Jeremiah 50 in the TNTIP

Jeremiah 50 in the TNTIZ

Jeremiah 50 in the TOMA

Jeremiah 50 in the TTENT

Jeremiah 50 in the UBG

Jeremiah 50 in the UGV

Jeremiah 50 in the UGV2

Jeremiah 50 in the UGV3

Jeremiah 50 in the VBL

Jeremiah 50 in the VDCC

Jeremiah 50 in the YALU

Jeremiah 50 in the YAPE

Jeremiah 50 in the YBVTP

Jeremiah 50 in the ZBP